ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 12/05 ojú ìwé 4
  • Àtúnyẹ̀wò Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àtúnyẹ̀wò Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
km 12/05 ojú ìwé 4

Àtúnyẹ̀wò Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run

Àwọn ìbéèrè tó wà nísàlẹ̀ wọ̀nyí la óò gbé yẹ̀ wò nínú àtúnyẹ̀wò aláfẹnusọ ní Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run, ní ọ̀sẹ̀ tó bẹ̀rẹ̀ ní December 26, 2005. Alábòójútó ilé ẹ̀kọ́ yóò darí àtúnyẹ̀wò yìí fún ọgbọ̀n ìṣẹ́jú, èyí tá a gbé ka àwọn iṣẹ́ ilé ẹ̀kọ́ tá a ṣe ní ọ̀sẹ̀ November 7 sí December 26, 2005. [Àkíyèsí: Níbi tí a kò bá ti tọ́ka sí ibi tí a ti mú ìdáhùn jáde lẹ́yìn ìbéèrè kan, o ní láti ṣe ìwádìí fúnra rẹ láti wá ìdáhùn sí ìbéèrè náà.—Wo ìwé Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run, ojú ìwé 36 sí 37.]

ÀNÍMỌ́ Ọ̀RỌ̀ SÍSỌ

1. Kí la lè ṣe ká bàa lè rí i dájú pé “nítorí ìfẹ́” la fi ń gbani níyànjú? (Fílém. 9) [be-YR ojú ìwé 266]

2. Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà “gbani níyànjú pẹ̀lú ẹ̀kọ́ afúnni-nílera”? (Títù 1:9) [be-YR ojú ìwé 267, ìpínrọ̀ 1 sí 2]

3. Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wa máa fún àwọn èèyàn níṣìírí, ọ̀nà wo la sì lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀? [be-YR ojú ìwé 268, ìpínrọ̀ 1 sí 3 àti àpótí]

4. Bíi ti Mósè, báwo ni rírán àwọn ará létí ohun tí Jèhófà ti ṣe lè fún wọn nígboyà? (Diu. 3:28; 31:1-8) [be-YR ojú ìwé 268, ìpínrọ̀ 5 sí ojú ìwé 269, ìpínrọ̀ 2]

5. Bá a bá ń fìdùnnú sọ̀rọ̀ nípa ohun tí Jèhófà ń ṣe nísinsìnyí àti ohun tó máa ṣe lọ́jọ́ iwájú, kí nìdí tó fi máa fún àwùjọ tá à ń bá sọ̀rọ̀ níṣìírí? [be-YR ojú ìwé 270 sí 271]

IṢẸ́ AKẸ́KỌ̀Ọ́ KÌÍNÍ

6. Báwo la ṣe lè fáwọn tá a jọ jẹ́ onígbàgbọ́ lókun? [w03-YR 5/15 ojú ìwé 22, ìpínrọ̀ 5 sí ojú ìwé 23, ìpínrọ̀ 2]

7. Irú ọrẹ wo ni inú Ọlọ́run dùn sí? [w03-YR 6/1 ojú ìwé 5, ìpínrọ̀ 2]

8. Báwo lèèyàn ṣe ń kọ́ bá a ṣeé nífẹ̀ẹ́? [w03-YR 7/1 ojú ìwé 4, ìpínrọ̀ 1; ojú ìwé 5, ìpínrọ̀ 4]

9. Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà ṣoore fáwọn ẹlòmíràn? (Gál. 6:9, 10) [w03-YR 7/15 ojú ìwé 7, ìpínrọ̀ 2 sí 3]

10. Mẹ́nu kan àwọn ìlànà mẹ́ta látinú Bíbélì tó lè ranni lọ́wọ́ láti ṣe àwọn ìpinnu tó mọ́gbọ́n dání. [w03-YR 10/15 ojú ìwé 4 sí 5]

BÍBÉLÌ KÍKÀ Ọ̀SỌ̀Ọ̀SẸ̀

11. Ǹjẹ́ ti pé Jèhófà ò jẹ́ kí Dáfídì kọ́ tẹ́ńpìlì fi hàn pé kò fọwọ́ sí àwọn ogun tí Dáfídì jà? (1 Kíró. 22:6-10)

12. Nínú àdúrà tí Sólómọ́nì gbà nígbà tó ń ya tẹ́ńpìlì sí mímọ́, báwo ló ṣe fi hàn pé yàtọ̀ sí pé Jèhófà máa ń gbọ́ tàwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lápapọ̀, ó tún mọ ipò tó ń dojú kọ ẹnì kọ̀ọ̀kan lára àwọn tó bẹ̀rù rẹ̀? (2 Kíró. 6:29, 30)

13. Kí ni “àwọn ẹ̀mí èṣù onírìísí ewúrẹ́” tí 2 Kíróníkà 11:15 mẹ́nu bà?

14. Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé “ní ọdún kẹta Ásà” ni Bááṣà bẹ̀rẹ̀ sí ṣàkóso, tó sì ṣàkóso fún ọdún mẹ́rìnlélógún péré, báwo wá ló ṣe lè jẹ́ pé “ní ọdún kẹrìndínlógójì ìgbà ìjọba Ásà” ni Bááṣà lọ “gbéjà ko Júdà”? (1 Ọba 15:33; 2 Kíró. 16:1)

15. Lọ́nà tó ṣe kedere, báwo ni 2 Kíróníkà 20:22, 23 ṣe ṣàpèjúwe ohun tó máa tó ṣẹlẹ̀ sí ayé Sátánì?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́