February 13-19
Aísáyà 52-57
Orin 148 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Kristi Jìyà fún Wa”: (10 min.)
Ais 53:3-5—Wọ́n tẹ́ńbẹ́lú rẹ̀, wọ́n sì tẹ̀ ẹ́ rẹ́ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa (w09 1/15 26 ¶3-5)
Ais 53:7, 8—Ó fẹ̀mí ara rẹ̀ rúbọ fún wa tinútinú (w09 1/15 27 ¶10)
Ais 53:11, 12—Àwa náà lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Ọlọ́run torí pé Jésù jẹ́ olóòótọ́ títí dójú ikú (w09 1/15 28 ¶13)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
Ais 54:1—Ta ni “àgàn tí kò bímọ” tí àsọtẹ́lẹ̀ yìí tọ́ka sí, àwọn wo sì ni “àwọn ọmọ” rẹ̀? (w06 3/15 11 ¶2)
Ais 57:15—Kí ni Jèhófà ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé òun ń “gbé” pẹ̀lú “àwọn tí a tẹ̀ rẹ́” àti “àwọn ẹni rírẹlẹ̀”? (w05 10/15 26 ¶3)
Ẹ̀kọ́ wo ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ mi nípa Jèhófà?
Àwọn kókó wo látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí ni mo lè lò lóde ẹ̀rí?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Ais 57:1-11
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Nígbà Àkọ́kọ́: (2 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) ll 6—Jẹ́ kí onílé mọ̀ pé o máa pa dà wá.
Ìpadàbẹ̀wò: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) ll 7—Jẹ́ kí onílé mọ̀ pé o máa pa dà wá.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì: (6 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) bh 14-15 ¶16-17—Tó bá ṣeé ṣe, ẹ jẹ́ kí bàbá kan bá ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́.
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
“Ran Àwọn Ọmọ Rẹ Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Ní Ìgbàgbọ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Nínú Ẹlẹ́dàá”: (15 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ káwọn ará wo fídíò yìí Ohun Táwọn Ojúgbà Rẹ Sọ—Ọlọ́run Wà Lóòótọ́.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) kr orí 8 ¶8-13 àti “Àtẹ Àwọn Ìwé Tí Wọ́n Ń Tẹ̀ Jáde Jù Láyé”
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 107 àti Àdúrà