ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g 7/13 ojú ìwé 3
  • Ohun Tó Ń Lọ Láyé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tó Ń Lọ Láyé
  • Jí!—2013
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà
  • Orílẹ̀-èdè Brazil
  • Orílẹ̀-èdè Norway
  • Orílẹ̀-èdè Czech Republic
  • Orílẹ̀-èdè Íńdíà
  • Ohun Tó Ń Lọ Láyé
    Jí!—2013
  • Bí Ọkàn Rẹ Ṣe Lè Balẹ̀ Nínú Ọkọ̀ Òfuurufú
    Jí!—2002
  • Gúúsù Ìlà Oòrùn Éṣíà
    Jí!—2014
  • Ohun Tó Ń Lọ Láyé
    Jí!—2013
Àwọn Míì
Jí!—2013
g 7/13 ojú ìwé 3

OHUN TÓ Ń LỌ LÁYÉ

Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Àwọn tó ń bójú tó ààbò ní pápákọ̀ òfuurufú lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà sọ pé ní ọdún mẹ́wàá tó kọjá, oríṣiríṣi nǹkan tí ìjọba fòfin dè, tó lé ní àádọ́ta [50] mílíọ̀nù làwọn òṣìṣẹ́ ààbò ti gbà lọ́wọ́ àwọn èèyàn nígbà tí wọ́n fẹ́ wọnú bàlúù. Lọ́dún 2011 nìkan, iye ìbọn tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn èèyàn lé ní ẹgbẹ̀fà [1,200]. Ọ̀pọ̀ àwọn tí wọ́n gba ìbọn lọ́wọ́ wọn sọ pé àwọn gbàgbé rẹ̀ sọ́wọ́ ni.

Orílẹ̀-èdè Brazil

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Àwọn aláṣẹ ilé ẹ̀kọ́ ti bẹ̀rẹ̀ sí í fi nǹkan kan sára aṣọ iléèwé àwọn ọmọ, èyí tí yóò máa fi àtẹ̀jíṣẹ́ ránṣẹ́ sáwọn òbí tí àwọn ọmọ bá sá kúrò níléèwé. Àwọn òbí máa ń rí àtẹ̀jíṣẹ́ gbà tó máa sọ ìgbà tọ́mọ wọn dé iléèwé, wọ́n á sì tún rí àtẹ̀jíṣẹ́ míì gbà tó bá ṣẹlẹ̀ pé ọmọ náà fi ogún [20] ìṣẹ́jú pẹ́ dé iléèwé.

Orílẹ̀-èdè Norway

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Lórílẹ̀-èdè Norway, ẹ̀sìn Ṣọ́ọ̀ṣì Luther kì í ṣe ẹ̀sìn tí ìjọba ní kí gbogbo èèyàn máa ṣe mọ́. Ìgbà àkọ́kọ́ nìyí tí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Orílẹ̀-èdè Norway ṣe àyípadà sí òfin tó fi dandan lé àjọṣe tó wà láàárín Ìjọba àti Ṣọ́ọ̀ṣì Luther.

Orílẹ̀-èdè Czech Republic

Ìwádìí fi hàn pé ìdá méjì nínú mẹ́ta àwọn òṣìṣẹ́ tó wà lórílẹ̀-èdè Czech Republic ló máa ń di ọ̀ranyàn fún láti gba ìpè tó jẹ mọ́ iṣẹ́ wọn lẹ́yìn tí wọ́n bá ti kúrò níbiṣẹ́, wọ́n tún máa ń gba lẹ́tà orí Íńtánẹ́ẹ̀tì tàbí àtẹ̀jíṣẹ́ pàápàá. O ju ìdá kan nínú mẹ́ta lọ lára wọn tó máa ń fẹ́ láti rí i pé wọ́n dá èsì pa dà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.

Orílẹ̀-èdè Íńdíà

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé oúnjẹ tí wọ́n ń mú jáde lórílẹ̀-èdè Íńdíà fi nǹkan bí ìdajì pọ̀ ju ti ogún [20] ọdún sẹ́yìn lọ, tí wọ́n sì tún ń tọ́jú mílíọ̀nù mọ́kànléláàádọ́rin [71] tọ́ọ̀nù ìrẹsì àti àlìkámà, síbẹ̀, ọ̀pọ̀ èèyàn lórílẹ̀-èdè náà ni kò rí oúnjẹ jẹ. Nǹkan bí ìdá mẹ́rin nínú mẹ́wàá àwọn oúnjẹ oníhóró tí wọ́n ń kó tọ́jú ló ń dé ọ̀dọ̀ àwọn aráàlù. Ìwà ìbàjẹ́ àti fífi nǹkan ṣòfò wà lára ohun tó fa ìṣòro wọn.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́