ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g16 No. 4 ojú ìwé 6
  • 3 Má Ṣe Jẹ́ Kó Sú Ẹ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • 3 Má Ṣe Jẹ́ Kó Sú Ẹ
  • Jí!—2016
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ọwọ́ Ẹ Lè Tẹ Àwọn Àfojúsùn Ẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Jẹ́ Kí Àwọn Àṣà Tó Ti Mọ́ Ọ Lára Ṣe Ọ́ Láǹfààní
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • Àwọn Àṣà Tó Lè Ṣe Ẹ́ Láǹfààní
    Jí!—2016
  • Báwo Ni Ọwọ́ Mi Ṣe Lè Tẹ Àwọn Ohun Tí Mo Fẹ́ Lé Bá?
    Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè—Àwọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́, Apá Kìíní
Àwọn Míì
Jí!—2016
g16 No. 4 ojú ìwé 6
Obìnrin kan tó ń fàmì sára kàlẹ́ńdà

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ÀWỌN ÀṢÀ TÓ LÈ ṢE Ẹ́ LÁǸFÀÀNÍ

3 Má Ṣe Jẹ́ Kó Sú Ẹ

Kàlẹ́ńdà tí wọ́n ti fàmì sí

Ọ̀pọ̀ gbà gbọ́ pé ó máa ń gbà tó ọjọ́ mọ́kànlélógún [21] kí ìwà kan tó lè mọ́ọ̀yàn lára. Àmọ́ ká sòótọ́, ìwádìí fi hàn pé àwọn míì kì í pẹ́ tó bẹ́ẹ̀, àwọn míì sì máa ń pẹ́ jù bẹ́ẹ̀ lọ kí nǹkan tó mọ́ wọn lára. Ṣé ó wá yẹ kí èyí mú ọ rẹ̀wẹ̀sì?

Ronú nípa àpẹẹrẹ yìí ná: Ká sọ pé ó wù ẹ́ láti máa ṣe eré ìmárale nígbà mẹ́ta lọ́sẹ̀.

  • Lọ́sẹ̀ àkọ́kọ́, ó ṣe dáadáa.

  • Lọ́sẹ̀ kejì, o pa ọjọ́ kan jẹ.

  • Lọ́sẹ̀ kẹta, o tún ṣe dáadáa.

  • Lọ́sẹ̀ kẹrin, ekukáká ló fi ṣe é lọ́jọ́ kan.

  • Lọ́sẹ̀ karùn-ún, o tún ṣe dáadáa, látìgbà yẹn lọ o kò pa ọjọ́ kankan jẹ mọ́.

Ó gba ọ̀sẹ̀ márùn-ún kí àṣà tuntun náà tó mọ́ ẹ lára. Ó lè jọ pé ó pẹ́ gan-an kó tó mọ́ ẹ lára, àmọ́ inú rẹ á dùn pé ọwọ́ rẹ ti tẹ ohun tó o fẹ́.

ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ: “Olódodo lè ṣubú ní ìgbà méje pàápàá, yóò sì dìde dájúdájú.”​—Òwe 24:16.

Bíbélì gbà wá níyànjú pé ká má ṣe jẹ́ kó sú wa. Kì í ṣe iye ìgbà tá a ṣubú ló ṣe pàtàkì jù, bí kò ṣe iye ìgbà tá a pa dà dìde.

Kì í ṣe iye ìgbà tá a ṣubú ló ṣe pàtàkì jù, bí kò ṣe iye ìgbà tá a pa dà dìde

OHUN TÓ O LÈ ṢE

  • Má ṣe parí èrò sí pé o ti di aláṣetì torí pé ọwọ́ rẹ kò tètè tẹ ohun tó o fẹ́. Wàá máa rí ìfàsẹ́yìn lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan bó o ṣe ń sapá láti lé àfojúsùn rẹ bá.

  • Ìgbà tí nǹkan lọ bó o ṣe fẹ́ ni kó o máa rò. Bí àpẹẹrẹ, tó bá jẹ́ pé ńṣe lo fẹ́ mú kí ọ̀nà tó ò ń gbà bá àwọn ọmọ rẹ sọ̀rọ̀ dára sí i, bí ara rẹ pé: ‘Ìgbà wo ló ṣe mí bíi kí n jágbe mọ́ àwọn ọmọ mi, àmọ́ tí mi ò ṣe bẹ́ẹ̀? Kí ni mo ṣe dípò ìyẹn? Báwo ni mo ṣe lè ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà míì?’ Irú àwọn ìbéèrè báyìí máa jẹ́ kó o lè ronú lórí àwọn àṣeyọrí rẹ dípò àwọn ìfàsẹ́yìn tó o ní.

Ṣé o fẹ́ mọ àwọn ọ̀nà míì tí Bíbélì lè gbà ràn ẹ́ lọ́wọ́, bóyá láti borí àníyàn, bí ìdílé rẹ ṣe lè láyọ̀, àti bó o ṣe lè ní ayọ̀ tó jinlẹ̀? Bá ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà sọ̀rọ̀ tàbí kó o lọ sórí ìkànnì wa, ìyẹn jw.org.

ÀWỌN ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ MÍÌ

“Ní ti ojú rẹ, ọ̀kánkán tààrà ni kí ó máa wò.”​—Òwe 4:25.

“Èmi a máa gbàgbé ohun gbogbo tí ó ti kọjá, èmi a sì máa nàgà láti mú ohun tí ó wà níwájú. Mò ń làkàkà láti dé òpin iré-ìje mi.”​—Fílípì 3:13, 14, Bibeli Ìròyìn Ayọ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́