ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g22 No. 1 ojú ìwé 4-6
  • 1 | Tọ́jú Ara Rẹ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • 1 | Tọ́jú Ara Rẹ
  • Jí!—2022
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ
  • Ohun Tó Yẹ Kó O Mọ̀
  • Ohun To O Lè Ṣe Ní Báyìí
  • Ohun Tó Máa Mú Kí Ìlera Rẹ Dára Sí I
    Jí!—2015
  • Ohun Tó O Lè Ṣe Tí Àìsàn Bá Dé Láìròtẹ́lẹ̀
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • Bóo Ṣe Lè Dáàbò Bo Ìlera Rẹ
    Jí!—1999
  • Ìlera Tó Dáa
    Jí!—2019
Àwọn Míì
Jí!—2022
g22 No. 1 ojú ìwé 4-6
Oríṣiríṣi oúnjẹ aṣaralóore wà lórí tábìlì.

AYÉ DOJÚ RÚ

1 | Tọ́jú Ara Rẹ

ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ

Tí àjálù bá ṣẹlẹ̀ tàbí tí wàhálà bá wà nílùú, onírúurú ọ̀nà nìyẹn máa ń gbà ṣàkóbá fún ìlera àwọn èèyàn.

  • Bí àpẹẹrẹ, àyà àwọn èèyàn sábà máa ń já tí wàhálà bá ṣẹlẹ̀, tí wọn ò bá sì tètè gbé ọ̀rọ̀ náà kúrò lọ́kàn, ìyẹn lè mú kí wọ́n ṣàìsàn.

  • Tí nǹkan ò bá rí bó ṣe yẹ kó rí nílùú, ìyẹn lè ṣàkóbá fún ètò ìlera débi pé kò ní rọrùn láti tọ́jú àwọn aláìsàn.

  • Tí àjálù bá ṣẹlẹ̀, ìyẹn lè má jẹ́ káwọn èèyàn rówó ra oúnjẹ aṣaralóore, oògùn àtàwọn nǹkan pàtàkì míì.

Ohun Tó Yẹ Kó O Mọ̀

  • Tẹ́nì kan bá ń ṣàìsàn tó le gan-an tàbí tí ọkàn ẹ̀ ò balẹ̀, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ò ní lè ronú bó ṣe tọ́, ó sì lè máa ṣe àwọn nǹkan táá ṣàkóbá fún ìlera ẹ̀. Ìyẹn sì lè mú kí àìsàn tó ń ṣe é burú sí i.

  • Tẹ́nì kan bá ń ṣàìsàn tí kò sì tọ́jú ara ẹ̀, ńṣe ni àìsàn náà á máa burú sí i, ó sì lè gbẹ̀mí ẹ̀.

  • Tára ẹ bá le dáadáa, wàá lè ronú lọ́nà tó tọ́, wàá sì lè ṣèpinnu tó dáa nígbà ìṣòro.

  • Tó ò bá tiẹ̀ fi bẹ́ẹ̀ lówó lọ́wọ́ àwọn nǹkan kan wà tó o lè ṣe láti tọ́jú ara ẹ.

Ohun To O Lè Ṣe Ní Báyìí

Tí ọlọ́gbọ́n bá rí ohun kan tó lè pa á lára, á tètè wá nǹkan ṣe sí i. Ohun tó yẹ ká ṣe nìyẹn tó bá kan ọ̀rọ̀ ìlera wa. Tá a bá ń ṣe ìmọ́tótó bó ṣe yẹ, a ò ní tètè máa ṣàìsàn, tá a bá sì ṣàìsàn, kò ní le jù. Ó ṣe tán, wọ́n sọ pé ìmọ́tótó borí àrùn mọ́lẹ̀.

“A máa ń tọ́jú ara wa dáadáa a sì máa ń jẹ́ kí àyíká wa wà ní mímọ́ tónítóní. Ìyẹn jẹ́ ká dín iye tá à ń ná lórí ọ̀rọ̀ ìtọ́jú ara wa kù.”​—Andreas.a

a A ti yí àwọn orúkọ kan pa dà nínú ìwé yìí.

KÍ LỌ̀NÀ ÀBÁYỌ?​—Ohun Tó O Lè Ṣe

Tí àjálù bá ṣẹlẹ̀ tàbí tí nǹkan ò bá rí bó ṣe yẹ kó rí nílùú, o lè dáàbò bo ara ẹ tó o bá ń ṣe àwọn nǹkan yìí

MÁA ṢE ÌMỌ́TÓTÓ

Ọkùnrin kan ń fi ọṣẹ àti omi fọ ọwọ́.

Máa ṣe ìmọ́tótó

Bíbélì sọ pé: “Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fara pa mọ́.” (Òwe 22:3) Ronú nípa àwọn nǹkan tó lè ṣàkóbá fún ìlera ẹ, kó o sì gbìyànjú láti yẹra fún wọn.

  • Máa fi ọṣẹ àti omi fọ ọwọ́ rẹ déédéé, ní pàtàkì kó o tó fọwọ́ kan oúnjẹ tàbí lẹ́yìn tó o bá ṣègbọ̀nsẹ̀.

  • Máa rí i pé ilé ẹ ń wà ní mímọ́ tónítóní, kó o sì máa fi ọṣẹ apakòkòrò nu ibi táwọn èèyàn sábà máa ń fọwọ́ kàn.

  • Tó bá ṣeé ṣe, máa jìnnà sáwọn tó bá ní àrùn tó ń ranni.

MÁA JẸ OÚNJẸ AṢARALÓORE

Oríṣiríṣi oúnjẹ aṣaralóore wà lórí tábìlì.

Máa jẹ oúnjẹ aṣaralóore

Bíbélì sọ pé: “Kò sí èèyàn kankan tó jẹ́ kórìíra ara rẹ̀, àmọ́ á máa bọ́ ara rẹ̀, á sì máa ṣìkẹ́ rẹ̀.” (Éfésù 5:29) Tá a bá ń ṣọ́ ohun tá à ń jẹ, ńṣe là ń fi hàn pé a mọyì ara wa, a sì ń ṣìkẹ́ rẹ̀.

  • Máa mumi dáadáa.

  • Máa jẹ oríṣiríṣi èso àti ẹ̀fọ́.

  • Dín bó o ṣe ń jẹ iyọ̀, ṣúgà àti ọ̀rá ẹran kù.

  • Yẹra fún sìgá, igbó, tábà àtàwọn nǹkan bẹ́ẹ̀, má sì ṣe mu ọtí lámujù tàbí lo oògùn nílòkulò.

“A máa ń jẹ oúnjẹ aṣaralóore ká má bàa ṣàìsàn, torí tá ò bá ṣe bẹ́ẹ̀, ṣe la máa fi ìwọ̀nba owó tó ń wọlé fún wa tọ́jú àìsàn. Ó sàn ká náwó lórí oúnjẹ aṣaralóore ju ká fi ra oògùn.”​—Carlos.

MÁA ṢE ERÉ ÌMÁRALE KÓ O SÌ MÁA SINMI DÁADÁA

Ọkùnrin kan ń sáré díẹ̀díẹ̀ lójú ọ̀nà eléruku kan.

Máa ṣe eré ìmárale

Bíbélì sọ pé: “Ẹ̀kúnwọ́ kan ìsinmi sàn ju ẹ̀kúnwọ́ méjì iṣẹ́ àṣekára àti lílé ohun tó jẹ́ ìmúlẹ̀mófo.” (Oníwàásù 4:6) Ó dáa ká ṣiṣẹ́ lóòótọ́, àmọ́ ó tún yẹ ká máa wáyè láti sinmi.

  • Máa ṣe ohun táá mú kára ẹ le. Bí àpẹẹrẹ, o lè ṣètò láti máa rin ìrìn ìṣẹ́jú bíi mélòó kan lójúmọ́. Ì báà jẹ́ àgbàlagbà ni ẹ́, aláàbọ̀ ara tàbí ẹni tó ń ṣàìsàn tó le gan-an, tó o bá ń ṣe eré ìmárale ìlera ẹ á túbọ̀ dáa sí i.

  • Obìnrin kan ń rẹjú.

    Máa sinmi dáadáa

    Máa sinmi dáadáa. Tẹ́nì kan ò bá ń sinmi dáadáa, ọpọlọ ẹ̀ ò ní ṣiṣẹ́ bó ṣe yẹ, kò sì ní lè pọkàn pọ̀. Tó bá sì ń bá a lọ bẹ́ẹ̀, ìyẹn lè yọrí sí àìsàn tó le gan-an.

  • Ní àkókò kan pàtó tí wàá máa sùn, tí wàá sì máa jí lójoojúmọ́, kó o sì rí i pé o ò jẹ́ kó yẹ̀.

  • Tó o bá fẹ́ sùn, má ṣe máa wo tẹlifíṣọ̀n tàbí lo àwọn ẹ̀rọ ìgbàlódé míì lórí ibùsùn rẹ.

  • Kó o tó lọ sùn, má ṣe jẹ oúnjẹ tí ò ní tètè dà tàbí mu ọtí, má sì ṣe jẹ ohunkóhun tó ní èròjà kaféènì, irú bí obì.

“Mo ti wá rí i pé oorun ṣe pàtàkì gan-an tí mo bá fẹ́ ní ìlera tó dáa. Tí mi ò bá sùn dáadáa, ṣe lorí á máa fọ́ mi, mi ò sì ní gbádùn ara mi. Àmọ́ tí mo bá sùn dáadáa, ṣe ni màá máa ta kébékébé, mi ò sì ní máa ṣàìsàn lemọ́lemọ́.”​—Justin.

Àwòrán apá kan látinú fídíò “Ohun Tó O Lè Ṣe tí Àjàkálẹ̀ Àrùn Bá Ṣẹlẹ̀.” Obìnrin kan ṣí ilẹ̀kùn iwájú ilé ẹ̀ sílẹ̀ kí kòkòrò àrùn lè wọlé.

KẸ́KỌ̀Ọ́ SÍ I. Wo fídíò náà Ohun Tó O Lè Ṣe tí Àjàkálẹ̀ Àrùn Bá Ṣẹlẹ̀. O tún lè ka àpilẹ̀kọ náà “Ohun Tó Máa Mú Kí Ìlera Rẹ Dára Sí I.” Wá àpilẹ̀kọ náà lórí ìkànnì jw.org.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́