ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • rq ẹ̀kọ́ 2 ojú ìwé 4-5
  • Ta Ni Ọlọrun?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ta Ni Ọlọrun?
  • Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣó Yẹ Ká Máa Fi Ère Jọ́sìn Ọlọ́run?
    Jí!—2008
  • Ohun Tó Jẹ́ Òtítọ́ Nípa Ọlọ́run àti Kristi
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2020
  • Ta Ni Ọlọ́run?
    Ìròyìn Ayọ̀ Látọ̀dọ̀ Ọlọ́run!
  • Ta Ni Ọlọ́run?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
Àwọn Míì
Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
rq ẹ̀kọ́ 2 ojú ìwé 4-5

Ẹ̀kọ́ 2

Ta Ni Ọlọrun?

Ta ni Ọlọrun tòótọ́ náà, kí sì ni orúkọ rẹ̀? (1, 2)

Irú ara wo ni òún ní? (3)

Àwọn ànímọ́ títa yọ wo ni òún ní? (4)

Ó ha yẹ kí á lo àwọn ère àti àmì ìjọsìn nínú ìjọsìn wa sí i bí? (5)

Àwọn ọ̀nà méjì wo ni a lè gbà kẹ́kọ̀ọ́ nípa Ọlọrun? (6)

1. Ọ̀pọ̀ nǹkan ni àwọn ènìyàn ń jọ́sìn. Ṣùgbọ́n, Bibeli sọ fún wa pé, Ọlọrun TÒÓTỌ́ kan ṣoṣo ni ó wà. Òun ni ó dá ohun gbogbo lókè ọ̀run àti lórí ilẹ̀ ayé. Nítorí pé òun ni ó fún wa ní ìwàláàyè, òun ni Ẹnì kan ṣoṣo tí a ní láti ­jọ́sìn.​—⁠1 Korinti 8:​5, 6; Ìṣípayá 4:⁠11.

2. Ọlọrun ní ọ̀pọ̀ orúkọ oyè, ṣùgbọ́n orúkọ kan ṣoṣo ni ó ní. JEHOFA ni orúkọ yẹn. Nínú ọ̀pọ̀ Bibeli, a ti yọ orúkọ Ọlọrun kúrò, a sì ti fi orúkọ oyè bíi OLUWA tàbí ỌLỌRUN rọ́pò rẹ̀. Ṣùgbọ́n nígbà tí a kọ Bibeli, orúkọ náà, Jehofa, fara hàn nínú rẹ̀ ní nǹkan bí ìgbà 7,000!​—⁠Eksodu 3:15; Orin Dafidi 83:⁠18.

3. Jehofa ní ara, ṣùgbọ́n kì í ṣe bíi tiwa. Bibeli sọ pé: “Ọlọrun jẹ́ Ẹ̀mí.” (Johannu 4:24) Ẹ̀mí jẹ́ oríṣi ìwàláàyè kan, tí ó ga fíofío ju tiwa lọ. Kò sí ènìyàn ­kankan tí ó tí ì rí Ọlọrun rí. Ọ̀run ni Jehofa ń gbé, ṣùgbọ́n ó lè rí ohun gbogbo. (Orin Dafidi 11:​4, 5; Johannu 1:18) Nígbà náà, kí ni ẹ̀mí mímọ́? Kì í ṣe ẹnì kan bí Ọlọrun. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó jẹ́ ipá agbékánkánṣiṣẹ́ Ọlọrun.​—⁠Orin Dafidi 104:⁠30.

4. Bibeli ṣí ànímọ́ Jehofa payá fún wa. Ó fi hàn pé ìfẹ́, ìdájọ́ òdodo, ọgbọ́n, àti agbára jẹ́ àwọn ànímọ́ rẹ̀ títa yọ. (Deuteronomi 32:⁠4; Jobu 12:13; Isaiah 40:26; 1 Johannu 4:⁠8) Bibeli sọ fún wa pé, òún jẹ́ aláàánú, onínúure, olùdáríjini, ọ̀làwọ́, àti onísùúrù pẹ̀lú. Àwa, gẹ́gẹ́ bí ọmọ onígbọràn, gbọ́dọ̀ gbìyànjú láti fara wé e.​—⁠Efesu 5:​1, 2.

5. Ó ha yẹ kí á tẹrí ba tàbí gbàdúrà sí ère, àwòrán, tàbí àmì ìjọsìn nínú ìjọsìn wa bí? Rárá! (Eksodu 20:​4, 5) Jehofa sọ pé òun nìkan ṣoṣo ni a gbọ́dọ̀ jọ́sìn. Òun kì yóò ṣàjọpín ògo rẹ̀ pẹ̀lú ẹlòmíràn tàbí ohun mìíràn. Ère kò ní agbára láti ràn wá lọ́wọ́.​—⁠Orin Dafidi 115:​4-⁠8; Isaiah 42:⁠8.

6. Báwo ni a ṣe lè mọ Ọlọrun dáradára sí i? Ọ̀nà kan jẹ́ nípa wíwo àwọn ohun tí òún ti dá, àti ríronú jinlẹ̀ nípa ohun tí wọ́n ń sọ fún wa. Àwọn ìṣẹ̀dá Ọlọrun ń fi hàn wá pé ó ní agbára àti ọgbọ́n gíga. A ń rí ìfẹ́ rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ti ṣe. (Orin Dafidi 19:​1-⁠6; Romu 1:20) Ọ̀nà míràn tí a lè gbà kẹ́kọ̀ọ́ nípa Ọlọrun jẹ́ nípa kíkẹ́kọ̀ọ́ Bibeli. Nínú rẹ̀, òún sọ púpọ̀ fún wa nípa irú Ọlọrun tí òún jẹ́. Ó tún sọ fún wa nípa ète rẹ̀ àti ohun tí òún fẹ́ kí a ṣe.​—⁠Amosi 3:⁠7; 2 Timoteu 3:​16, 17.

[Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 5]

A ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa Ọlọrun láti ara ìṣẹ̀dá àti láti inú Bibeli

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́