ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • rq ẹ̀kọ́ 15 ojú ìwé 30
  • Ríran Àwọn Ẹlòmíràn Lọ́wọ́ Láti Ṣe Ìfẹ́ Ọlọrun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ríran Àwọn Ẹlòmíràn Lọ́wọ́ Láti Ṣe Ìfẹ́ Ọlọrun
  • Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bó O Ṣe Lè Máa Wàásù Ìhìn Rere Fáwọn Èèyàn
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • ‘Àwọn Tí Ń mú Ìhìn Rere Ohun Tí Ó Dára Jù Wá’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Báwo La Ṣe Ń Wàásù Ìhìn Rere?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • Ṣé Ìwọ Náà Lè Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
Àwọn Míì
Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
rq ẹ̀kọ́ 15 ojú ìwé 30

Ẹ̀kọ́ 15

Ríran Àwọn Ẹlòmíràn Lọ́wọ́ Láti Ṣe Ìfẹ́ Ọlọrun

Èé ṣe tí ó fi yẹ kí o sọ nípa ohun tí o ń kọ́ fún àwọn ẹlòmíràn? (1)

Ta ni o lè bá ṣàjọpín ìhìn rere náà? (2)

Ipa wo ni ìwà rẹ lè ní lórí àwọn ẹlòmíràn? (2)

Nígbà wo ni o lè wàásù pẹ̀lú ìjọ? (3)

1. Ní báyìí, o ti kẹ́kọ̀ọ́ ọ̀pọ̀ ohun rere láti inú Bibeli. Ìmọ̀ yìí yẹ kí ó sún ọ sí mímú àkópọ̀ ìwà Kristian dàgbà. (Efesu 4:​22-⁠24) Irú ìmọ̀ bẹ́ẹ̀ ṣe kókó, kí o lè jèrè ìyè àìnípẹ̀kun. (Johannu 17:⁠3) Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn mìíràn pẹ̀lú ní láti gbọ́ ìhìn rere náà, kí àwọn pẹ̀lú lè rí ìgbàlà. Gbogbo Kristian tòótọ́ gbọ́dọ̀ wàásù fún àwọn ẹlòmíràn. Àṣẹ Ọlọrun ni.​—⁠Romu 10:10; 1 Korinti 9:16; 1 Timoteu 4:⁠16.

2. O lè bẹ̀rẹ̀ nípa ṣíṣàjọpín àwọn ohun rere tí o ń kọ́ pẹ̀lú àwọn tí wọ́n sún mọ́ ọ. Sọ wọ́n fún ìdílé, ọ̀rẹ́, àwọn ọmọ ilé ẹ̀kọ́, àti àwọn òṣìṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ. Jẹ́ onínúure àti onísùúrù, bí o ti ń ṣe bẹ́ẹ̀. (2 Timoteu 2:​24, 25) Máa fi í sọ́kàn pé, àwọn ènìyàn sábà máa ń wo ìwà ẹnì kan ju bí wọ́n ṣe ń fetí sí ohun tí ó ń sọ lọ. Nítorí náà, ìwà rere rẹ lè fa àwọn mìíràn mọ́ra láti tẹ́tí sí ìhìn iṣẹ́ tí o ń wàásù.​—⁠Matteu 5:16; 1 Peteru 3:​1, 2, 16.

3. Bí àkókò ti ń lọ, o lè tóótun láti bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù pẹ̀lú ìjọ àdúgbò, ti àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa. Èyí jẹ́ ìgbésẹ̀ pàtàkì kan nínú ìtẹ̀síwájú rẹ. (Matteu 24:14) Wo irú ìdùnnú tí yóò jẹ́ bí o bá lè ran ẹnì kan lọ́wọ́ láti di ìránṣẹ́ Jehofa, kí ó sì jèrè ìyè ayérayé!​—⁠1 Tessalonika 2:​19, 20.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́