ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • rq ẹ̀kọ́ 16 ojú ìwé 31
  • Ìpinnu Rẹ Láti Sin Ọlọrun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìpinnu Rẹ Láti Sin Ọlọrun
  • Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé O Ti Ṣe Tán Láti Ṣèrìbọmi?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Ìrìbọmi Ló Máa Fìdí Àjọṣe Rẹ Pẹ̀lú Ọlọ́run Múlẹ̀
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Ṣé Ó Yẹ Kí N Ya Ìgbésí Ayé Mi Sí Mímọ́ fún Ọlọ́run, Kí N sì Ṣe Ìrìbọmi?
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Fi Ṣe Góńgó-Ìlépa Rẹ Láti Ṣiṣẹ́sin Ọlọrun Títí Láé
    Ìmọ̀ Tí Ń Sinni Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun
Àwọn Míì
Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
rq ẹ̀kọ́ 16 ojú ìwé 31

Ẹ̀kọ́ 16

Ìpinnu Rẹ Láti Sin Ọlọrun

Kí ni o gbọ́dọ̀ ṣe láti lè di ọ̀rẹ́ Ọlọrun? (1, 2)

Báwo ni o ṣe lè ya ara rẹ sí mímọ́ fún Ọlọrun? (1)

Nígbà wo ni ó yẹ kí o ṣe ìrìbọmi? (2)

Báwo ni o ṣe lè jèrè okun láti máa bá ìṣòtítọ́ sí Ọlọrun nìṣó? (3)

1. Láti lè di ọ̀rẹ́ Ọlọrun, o gbọ́dọ̀ jèrè ìmọ̀ òtítọ́ Bibeli dáradára (1 Timoteu 2:​3, 4), lo ìgbàgbọ́ nínú àwọn ohun tí o ti kọ́ (Heberu 11:⁠6), ronú pìwà dà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ (Ìṣe 17:​30, 31), kí o sì yí ọ̀nà ìgbésí ayé rẹ padà. (Ìṣe 3:19) Lẹ́yìn náà, ìfẹ́ rẹ fún Ọlọrun gbọ́dọ̀ sún ọ láti ya ara rẹ sí mímọ́ fún un. Èyí túmọ̀ sí pé o ní láti sọ fún un nínú àdúrà ara ẹni rẹ, ní ­ìdákọ́ńkọ́ pé, o ń fi ara rẹ fún un láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀.​—⁠Matteu 16:24; 22:37.

2. Lẹ́yìn tí o bá ti ya ara rẹ sí mímọ́ fún Ọlọrun, o gbọ́dọ̀ ṣe ìrìbọmi. (Matteu 28:​19, 20) Ìrìbọmi ń jẹ́ kí gbogbo ènìyàn mọ̀ pé o ti ya ara rẹ sí mímọ́ fún Jehofa. Nítorí náà, ìrìbọmi wà fún kìkì àwọn tí wọ́n ti dàgbà tó láti pinnu láti sin Ọlọrun. Nígbà tí a bá ń batisí ẹnì kan, ­gbogbo ara rẹ̀ ni a gbọ́dọ̀ rì bọ inú omi fún àkókò díẹ̀.a​—⁠Marku 1:​9, 10; Ìṣe 8:⁠36.

3. Lẹ́yìn tí o bá ti ṣe ìyàsímímọ́, Jehofa yóò retí pé kí o máa gbé ní ìbámu pẹ̀lú ìlérí rẹ. (Orin Dafidi 50:14; Oniwasu 5:​4, 5) Eṣu yóò gbìyànjú láti dá ọ lọ́wọ́ kọ́ láti sin Jehofa. (1 Peteru 5:⁠8) Ṣùgbọ́n, sún mọ́ Ọlọrun pẹ́kípẹ́kí nínú àdúrà. (Filippi 4:​6, 7) Máa kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ rẹ̀ lójoojúmọ́. (Orin Dafidi 1:​1-⁠3) Rọ̀ mọ́ ìjọ tímọ́tímọ́. (Heberu 13:17) Nípa ṣíṣe gbogbo ìwọ̀nyí, ìwọ yóò jèrè okun láti máa bá ìṣòtítọ́ sí Ọlọrun nìṣó. O lè tipa báyìí máa ṣe àwọn ohun tí Ọlọrun ń béèrè lọ́wọ́ rẹ títí ayérayé!

[Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

a A dámọ̀ràn kíkẹ́kọ̀ọ́ ìwé Ìmọ̀ Tí Ń Sinni Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun, tàbí irú ìwé bẹ́ẹ̀, tí a tẹ̀ jáde láti ọwọ́ Watch Tower Bible and Tract Society, ní ìmúra sílẹ̀ fún ìrìbọmi.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́