APÁ 1
‘Agbára Rẹ̀ Ń Bani Lẹ́rù’
Nínú apá yìí, a máa ṣàyẹ̀wò àwọn ìtàn Bíbélì tó fi hàn pé Jèhófà lágbára láti ṣẹ̀dá, láti pani run, láti dáàbò boni àti láti mú nǹkan bọ̀ sípò. Bá a bá ṣe ń rí i pé ‘agbára Jèhófà ń bani lẹ́rù’ àti pé “okun rẹ̀ tó fi ń ṣiṣẹ́ pọ̀ yanturu,” ìyẹn á jẹ́ ká nígboyà, ìrètí wa á sì dájú.—Àìsáyà 40:26.