ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 14 ojú ìwé 40-ojú ìwé 41 ìpínrọ̀ 1
  • Ẹrú Tó Ṣègbọràn sí Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹrú Tó Ṣègbọràn sí Ọlọ́run
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ‘Èmi Kò Lè Hùwà Búburú Ńlá Yìí’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àwọn Ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù Kórìíra Rẹ̀
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Jèhófà Máa Jẹ́ Kó O Ṣàṣeyọrí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Wọ́n Ju Jósẹ́fù Sẹ́wọ̀n
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 14 ojú ìwé 40-ojú ìwé 41 ìpínrọ̀ 1
Jósẹ́fù sá kúrò lọ́dọ̀ ìyàwó Pọ́tífárì

Ẹ̀KỌ́ 14

Ẹrú Tó Ṣègbọràn sí Ọlọ́run

Nínú àwọn ọmọkùnrin méjìlá (12) tí Jékọ́bù bí, Jósẹ́fù ló jẹ́ ìkọkànlá (11). Àwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù rí i pé òun ni bàbá wọn fẹ́ràn jù. Ǹjẹ́ o mọ bó ṣe rí lára wọn? Ńṣe ni wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í jowú Jósẹ́fù, wọ́n sì kórìíra ẹ̀. Nígbà kan, Jósẹ́fù lá àwọn àlá kan tó ṣàrà ọ̀tọ̀. Nígbà tó sọ àwọn àlá náà fáwọn ẹ̀gbọ́n ẹ̀, inú wọn ò dùn, wọ́n rò pé ṣe ló ń dọ́gbọ́n sọ pé wọ́n máa tẹrí ba fóun lọ́jọ́ iwájú. Ìyẹn wá mú kí wọ́n túbọ̀ kórìíra ẹ̀.

Àwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù jù ú sínú kòtò

Lọ́jọ́ kan, àwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù kó àwọn àgùntàn wọn lọ jẹko nítòsí ìlú Ṣékémù. Jékọ́bù wá rán Jósẹ́fù pé kó lọ wò wọ́n láti mọ̀ bóyá àlàáfíà ni wọ́n wà. Nígbà táwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù rí i lọ́ọ̀ọ́kán, wọ́n sọ fún ara wọn pé: ‘Ọmọ tó máa ń lá àlá yẹn ló ń bọ̀ yẹn. Ẹ jẹ́ ká pa á!’ Wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò jíjìn. Àmọ́ ọ̀kan lára àwọn ẹ̀gbọ́n ẹ̀ tó ń jẹ́ Júdà sọ pé: ‘Ẹ má jẹ́ ká pa á! Ẹ jẹ́ ká tà á bí ẹrú.’ Torí náà, wọ́n ta Jósẹ́fù ní ogún (20) owó fàdákà fáwọn oníṣòwò Mídíánì tó ń lọ sí Íjíbítì.

Lẹ́yìn náà, àwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù mú aṣọ ẹ̀, wọ́n kì í sínú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́, wọ́n wá fi aṣọ náà ránṣẹ́ sí bàbá wọn, wọ́n sì sọ fún un pé: ‘Wo aṣọ yìí, ṣé kì í ṣe aṣọ Jósẹ́fù?’ Nígbà tí Jékọ́bù rí i, ó rò pé ẹranko kan ló pa Jósẹ́fù jẹ. Inú ẹ̀ bà jẹ́ débi pé kò sẹ́ni tó lè tù ú nínú.

Jósẹ́fù wà nínú ẹ̀wọ̀n

Nígbà táwọn oníṣòwò yẹn dé Íjíbítì, wọ́n ta Jósẹ́fù lẹ́rú fún olóyè kan tó ń jẹ́ Pọ́tífárì. Àmọ́, Jèhófà ò fi Jósẹ́fù sílẹ̀. Pọ́tífárì kíyè sí i pé Jósẹ́fù kì í fiṣẹ́ ṣeré àti pé ó ṣeé gbẹ́kẹ̀ lé. Bí Pọ́tífárì ṣe ní kó máa bójú tó gbogbo ilé òun nìyẹn.

Ìyàwó Pọ́tífárì kíyè sí i pé Jósẹ́fù jẹ́ ọkùnrin tó rẹwà, àti pé ó lágbára. Ojoojúmọ́ ló máa ń sọ fún Jósẹ́fù pé kó wá bá òun sùn. Kí ni Jósẹ́fù wá ṣe? Jósẹ́fù ò gbà, ó sọ fún obìnrin náà pé: ‘Rárá o! Mi ò ṣe. Ọkọ yín gbẹ́kẹ̀ lé mi, ẹ̀yin sì ni ìyàwó ẹ̀. Tí mo bá sùn tì yín, ẹ̀ṣẹ̀ ni lójú Ọlọ́run.’

Lọ́jọ́ kan, ìyàwó Pọ́tífárì fẹ́ fi dandan mú Jósẹ́fù kó lè bá a sùn. Ó di aṣọ Jósẹ́fù mú, àmọ́ Jósẹ́fù sá jáde. Nígbà tí Pọ́tífárì pa dà dé, obìnrin náà parọ́ mọ́ Jósẹ́fù, ó sọ fún ọkọ ẹ̀ pé Jósẹ́fù fẹ́ fipá bá òun sùn. Inú bí Pọ́tífárì gan-an, ó sì ní kí wọ́n ju Jósẹ́fù sẹ́wọ̀n. Síbẹ̀, Jèhófà ò gbàgbé Jósẹ́fù.

“Torí náà, ẹ rẹ ara yín sílẹ̀ lábẹ́ ọwọ́ agbára Ọlọ́run, kó lè gbé yín ga ní àkókò tó yẹ.”​—1 Pétérù 5:6

Ìbéèrè: Kí ni àwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù ṣe fún un? Kí ló dé tí wọ́n fi ju Jósẹ́fù sẹ́wọ̀n?

Jẹ́nẹ́sísì 37:1-36; 39:1-23; Ìṣe 7:9

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́