ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 90 ojú ìwé 210
  • Wọ́n Pa Jésù ní Gọ́gọ́tà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Wọ́n Pa Jésù ní Gọ́gọ́tà
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Pílátù àti Hẹ́rọ́dù Rí I Pé Jésù Ò Jẹ̀bi
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Lati Ọ̀dọ̀ Pilatu Sọdọ Hẹrọdu A sì Tún Rán an Pada
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • Ta Ni Pọ́ńtíù Pílátù?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Ó Fa Jésù Lé Wọn Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Lọ Pa Á
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 90 ojú ìwé 210
Jésù wà lórí òpó igi, ọmọ ogun kan, Màríà, Jòhánù àtàwọn ọmọlẹ́yìn Jésù mí ì dúró nítòsí

Ẹ̀KỌ́ 90

Wọ́n Pa Jésù ní Gọ́gọ́tà

Àwọn olórí àlùfáà mú Jésù lọ sáàfin gómìnà kan tó ń jẹ́ Pílátù. Nígbà tí Jésù débẹ̀, Pílátù bi àwọn àlùfáà náà pé: ‘Ohun búburú wo ni ọkùnrin yìí ṣe?’ Wọ́n dá a lóhùn pé: ‘Ó ń pe ara ẹ̀ lọ́ba!’ Pílátù wá bi Jésù pé: ‘Ṣé ìwọ ni Ọba àwọn Júù?’ Jésù dáhùn pé: “Ìjọba mi kì í ṣe apá kan ayé yìí.”

Ni Pílátù bá ní kí wọ́n mú Jésù lọ sọ́dọ̀ Hẹ́rọ́dù alákòóso Gálílì, bóyá ó máa mọ ẹ̀ṣẹ̀ tí Jésù ṣẹ̀. Àmọ́ Hẹ́rọ́dù náà ò rí ohun búburú kankan nípa Jésù, torí náà ó ní kí wọ́n mú un pa dà sọ́dọ̀ Pílátù. Pílátù wá sọ fáwọn èèyàn náà pé: ‘Èmi àti Hẹ́rọ́dù ò rí ohun búburú kankan nípa ọkùnrin yìí. Torí náà, màá tú u sílẹ̀ kó máa lọ.’ Àmọ́ àwọn èèyàn náà bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe pé: ‘Pa á! Pa á!’ Àwọn ọmọ ogun na Jésù lẹ́gba, wọ́n tutọ́ sí i lára, wọ́n sì ń gbá a ní ẹ̀ṣẹ́. Wọ́n tún ṣe adé ẹ̀gún, wọ́n fi dé orí ẹ̀, wọ́n sì fi ṣe yẹ̀yẹ́ pé: ‘Ẹ ǹlẹ́ o, Ọba àwọn Júù!’ Pílátù tún lọ bá àwọn èèyàn náà, ó sì sọ fún wọn pé: ‘Lójú tèmi, ọkùnrin yìí ò dẹ́ṣẹ̀ kankan.’ Ṣùgbọ́n wọ́n tún kígbe pé: “Kàn án mọ́gi!” Torí náà, Pílátù fa Jésù lé wọn lọ́wọ́ láti pa á.

Wọ́n mú Jésù lọ síbì kan tí wọ́n ń pè ní Gọ́gọ́tà, wọ́n kàn án mọ́ òpó igi kan, wọ́n wá gbé igi náà dúró. Jésù wá gbàdúrà pé: ‘Baba, dárí jì wọ́n torí wọn ò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe.’ Àwọn èèyàn ń fi Jésù ṣe yẹ̀yẹ́ pé: ‘Tó bá jẹ́ pé Ọmọ Ọlọ́run ni ẹ́, gba ara rẹ là kó o sì bọ́ sílẹ̀ lórí igi yìí.’

Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀daràn tí wọ́n kàn mọ́gi lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jésù sọ fún Jésù pé: “Rántí mi nígbà tó o bá dé inú Ìjọba ẹ.” Jésù sì ṣèlérí fún un pé: “O máa wà pẹ̀lú mi ní Párádísè.” Lọ́sàn-án ọjọ́ yẹn, òkùnkùn ṣú bo gbogbo ilẹ̀ náà fún wákàtí mẹ́ta. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọlẹ́yìn ẹ̀ dúró sẹ́gbẹ̀ẹ́ òpó igi tí wọ́n kan Jésù mọ́, Màríà ìyá Jésù náà wà pẹ̀lú wọn. Jésù wá sọ fún Jòhánù pé kó máa tọ́jú Màríà bí ìgbà tó ń tọ́jú ìyá ẹ̀ gangan.

Níkẹyìn, Jésù sọ pé: “A ti ṣe é parí!” Ó tẹ orí ẹ̀ ba, ó sì kú. Lójijì, ilẹ̀ mì tìtì lọ́nà tó lágbára. Ohun ìyanu kan sì ṣẹlẹ̀ nínú tẹ́ńpìlì, aṣọ ńlá kan tó wà láàárín Ibi Mímọ́ àti Ibi Mímọ́ Jù lọ ya sí méjì látòkè délẹ̀. Ọ̀kan lára àwọn ọmọ ogun tó wà níbẹ̀ wá sọ pé: ‘Dájúdájú Ọmọ Ọlọ́run nìyí.’

“Bó ṣe wù kí àwọn ìlérí Ọlọ́run pọ̀ tó, wọ́n ti di ‘bẹ́ẹ̀ ni’ nípasẹ̀ rẹ.”​—2 Kọ́ríńtì 1:20

Ìbéèrè: Kí nìdí tí Pílátù fi jẹ́ kí wọ́n pa Jésù? Báwo ni Jésù ṣe fi hàn pé ọ̀rọ̀ àwọn míì ṣe pàtàkì sí òun ju ti ara òun lọ?

Mátíù 27:11-14, 22-31, 38-56; Máàkù 15:2-5, 12-18, 25, 29-33, 37-39; Lúùkù 23:1-25, 32-49; Jòhánù 18:28–19:30

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́