ORIN 131
‘Ohun Tí Ọlọ́run So Pọ̀’
Bíi Ti Orí Ìwé
1. Jáà fìfẹ́ so wọ́n pọ̀;
Ọkàn wọn kún fáyọ̀.
Àwọn èèyàn jẹ́rìí sí i,
Bí wọ́n ṣe ń jẹ́jẹ̀ẹ́ wọn.
(ÈGBÈ 1)
Ọkọ jẹ́jẹ̀ẹ́ fáya pé:
‘Màá fẹ́ ọ látọkàn.’
‘Ohun t’Ọlọ́run so pọ̀,
Kéèyàn má ṣe yà wọ́n.’
2. Wọ́n kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì
Kí wọ́n lè ṣèfẹ́ Jáà.
Wọ́n ńbẹ̀bẹ̀ fún ‘rànwọ́ rẹ̀
Láti mẹ́jẹ̀ẹ́ wọn ṣẹ.
(ÈGBÈ 2)
Aya jẹ́jẹ̀ẹ́ fọ́kọ pé:
Màá fẹ́ ọ látọkàn.’
‘Ohun t’Ọlọ́run so pọ̀,
Kéèyàn má ṣe yà wọ́n.’
(Tún wo Jẹ́n. 2:24; Oníw. 4:12; Éfé. 5:22-33.)