ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w09 4/1 ojú ìwé 7-8
  • Kí Nìdí Táwọn Kan Fi Ní Láti Di Àtúnbí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Nìdí Táwọn Kan Fi Ní Láti Di Àtúnbí?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìwọ̀nba Làwọn Tó Máa Ṣàkóso, Ọ̀pọ̀ Ló Máa Jàǹfààní
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Ìjọba Ọlọrun Ń Ṣàkóso
    Ìmọ̀ Tí Ń Sinni Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
w09 4/1 ojú ìwé 7-8

Kí Nìdí Táwọn Kan Fi Ní Láti Di Àtúnbí?

Ọ̀PỌ̀ ló gbà gbọ́ pé téèyàn ò bá di àtúnbí kò lè nígbàlà. Àmọ́, jẹ́ ká wo ohun tí Jésù fúnra ẹ̀ sọ nípa ìdí téèyàn fi ní láti di àtúnbí. Ó sọ pé: “Láìjẹ́ pé a tún ẹnikẹ́ni bí, kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.” (Jòhánù 3:3) Torí náà, èèyàn ní láti di àtúnbí kó tó lè wọ Ìjọba Ọlọ́run, kì í ṣe kónítọ̀hún tó lè ní ìgbàlà. Àwọn míì lè sọ pé, ‘Ṣebí ohun kan náà ló túmọ̀ sí láti wọ Ìjọba Ọlọ́run àti láti nígbàlà?’ Rárá o, wọ́n yàtọ̀ síra. Ká lè mọ ìyàtọ̀ tó wà láàárín méjèèjì, ẹ jẹ́ ká kọ́kọ́ wo ohun tí “ìjọba Ọlọ́run” túmọ̀ sí.

Oríṣiríṣi ọ̀nà làwọn ìjọba gbà ń ṣàkóso, torí náà, “ìjọba Ọlọ́run” túmọ̀ sí “ìṣàkóso Ọlọ́run.” Bíbélì kọ́ni pé Jésù Kristi tó jẹ́ “ọmọ ènìyàn” ni Ọba Ìjọba Ọlọ́run àti pé Kristi láwọn tí wọ́n jọ máa ṣàkóso. (Dáníẹ́lì 7:1, 13, 14; Mátíù 26:63, 64) Yàtọ̀ síyẹn, ìràn kan tí àpọ́sítélì Jòhánù rí jẹ́ ká mọ̀ pé àwọn tó máa ṣàkóso pẹ̀lú Kristi jẹ́ onírúurú èèyàn tí Ọlọ́run yàn láti “inú gbogbo ẹ̀yà àti ahọ́n àti àwọn ènìyàn àti orílẹ̀-èdè,” wọ́n sì máa “ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí ọba lé ilẹ̀ ayé lórí.” (Ìṣípayá 5:9, 10; 20:6) Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tún jẹ́ ká mọ̀ pé àwọn tó máa jọba ló máa para pọ̀ di “agbo kékeré” tí iye wọn jẹ́ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000], àwọn yìí ni Ọlọ́run “ti rà láti ilẹ̀ ayé wá.”—Lúùkù 12:32; Ìṣípayá 14:1, 3.

Ibo ni Ìjọba Ọlọ́run á ti máa ṣàkóso wá? Bíbélì pe “ìjọba Ọlọ́run” ní “ìjọba ọ̀run,” ìyẹn sì jẹ́ ká mọ̀ pé látọ̀run wá ni Jésù àtàwọn tó máa jọba pẹ̀lú rẹ̀ ti máa ṣàkóso. (Lúùkù 8:10; Mátíù 13:11) Torí náà, tí Bíbélì bá ń sọ̀rọ̀ nípa Ìjọba Ọlọ́run, ìṣàkóso àtọ̀runwá látọwọ́ Jésù Kristi àtàwọn èèyàn tí Ọlọ́run yàn láti ṣàkóso pẹ̀lú rẹ̀ ló ń sọ.

Kí wá ni Jésù ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé èèyàn gbọ́dọ̀ di àtúnbí kó tó lè “wọ ìjọba Ọlọ́run”? Ohun tó ní lọ́kàn ni pé ẹnì kan ní láti di àtúnbí kó tó lè ṣàkóso pẹ̀lú òun lọ́run. Lọ́rọ̀ kan, ìdí tí Ọlọ́run fi ń sọ ìwọ̀nba àwọn èèyàn kan di àtúnbí ni pé kí wọ́n lè ṣàkóso lọ́run.

Látinú ìjíròrò wa, a ti rí i pé ó ṣe pàtàkì pé káwọn kan di àtúnbí, pé Ọlọ́run ló máa ń pinnu ẹni tó máa di àtúnbí àti pé dídi àtúnbí ń jẹ́ kó ṣeé ṣe fáwọn kan láti ṣàkóso lọ́run. Àmọ́, báwo lèèyàn ṣe lè di àtúnbí gan-an?

[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 7]

Ìdí tí Ọlọ́run fi ń sọ ìwọ̀nba àwọn èèyàn kan di àtúnbí ni pé kí wọ́n lè ṣàkóso lọ́run

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 7]

Jésù Kristi àtàwọn èèyàn tí Ọlọ́run yàn láti ṣàkóso pẹ̀lú rẹ̀ ló para pọ̀ di Ìjọba Ọlọ́run

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́