ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp20 No. 2 ojú ìwé 4-5
  • Kí Nìdí Tá A Fi Nílò Ìjọba Ọlọ́run?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Nìdí Tá A Fi Nílò Ìjọba Ọlọ́run?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2020
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • BÍ ÌJỌBA ÈÈYÀN ṢE BẸ̀RẸ̀
  • ÀKÓKÒ TÓ LÁTI YANJÚ ÀWỌN ÌṢÒRO NÁÀ!
  • Ìjọba Ọlọ́run—Ìṣàkóso Tuntun Fún Ilẹ̀ Ayé
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Àyè Tí Ọlọ́run Fi Gba Ìjìyà Ti Fẹ́rẹ̀ẹ́ Dópin
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • Ìṣàkóso Jèhófà Ló Dára Jù Lọ!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Kí Nìdí Tí Nǹkan Burúkú Fi Ń Ṣẹlẹ̀ Tá A sì Ń Jìyà?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2020
wp20 No. 2 ojú ìwé 4-5
Ádámù àti Éfà wà nínú ọgbà Édẹ́nì, wọ́n ń wo omi bó ṣe ń ya wálẹ̀ látorí òkè.

Nígbà tí àwọn èèyàn ṣì wà lábẹ́ àkóso Ọlọ́run, gbogbo ohun tí Ọlọ́run dá ló wà níṣọ̀kan àti ní àlàáfíà

Kí Nìdí Tá A Fi Nílò Ìjọba Ọlọ́run?

Ẹlẹ́dàá wa tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jèhófà nìkan ṣoṣo ni Alákòóso nígbà tó dá àwọn èèyàn àkọ́kọ́. Ó sì ń ṣàkóso lọ́nà tó fi ìfẹ́ hàn. Ó ṣe ibùgbé kan tó rẹwà gan-an fún àwọn èèyàn láti máa gbé, orúkọ rẹ̀ ni ọgbà Édẹ́nì. Ó sì pèsè oríṣiríṣi nǹkan tí wọ́n lè jẹ. Ó tún fún àwọn èèyàn ní iṣẹ́ tó dára láti máa ṣe. (Jẹ́nẹ́sísì 1:28, 29; 2:8, 15) Ká sọ pé àwa èèyàn gbà kí Ọlọ́run máa fìfẹ́ ṣàkóso wa lọ ni, à bá ṣì máa gbé ní àlàáfíà.

Ádámù mú èso tí Éfà fún un dání, èyí tí Jèhófà sọ pé wọn kò gbọ́dọ̀ jẹ.

Àwọn èèyàn tí Ọlọ́run kọ́kọ́ dá kò gbà kí Ọlọ́run máa jẹ́ Alákòóso wọn

Bíbélì sọ pé áńgẹ́lì ọlọ̀tẹ̀ kan wà tá a wá mọ̀ sí Sátánì Èṣù, tó pe Ọlọ́run níjà pé kò lẹ́tọ̀ọ́ láti máa ṣàkóso. Ohun tó ní lọ́kàn ni pé àwa èèyàn máa túbọ̀ láyọ̀ tá a bá ń ṣàkóso ara wa, láìjẹ́ pé Ọlọ́run ń darí wa. Ó dùn wá gan-an pé àwọn òbí wa àkọ́kọ́, Ádámù àti Éfà dara pọ̀ mọ́ Sátánì, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run.​—Jẹ́nẹ́sísì 3:​1-6; Ìfihàn 12:9.

Nítorí pé Ádámù àti Éfà ò gbà kí Ọlọ́run máa jẹ́ Alákòóso wọn, wọ́n pàdánù Párádísè, wọn ò sì nírètí mọ́ láti wà láàyè títí láé pẹ̀lú ìlera pípé. (Jẹ́nẹ́sísì 3:​17-19) Ohun tí wọ́n ṣe yìí tún ṣàkóbá fún àwọn ọmọ wọn. Bíbélì sọ pé nítorí pé Ádámù ṣẹ̀, ‘ẹ̀ṣẹ̀ wọ ayé, ikú sì wá nípasẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀.’ (Róòmù 5:12) Ẹ̀ṣẹ̀ tún fa àjálù míì, ohun tó yọrí sí ni pé: “Èèyàn ti jọba lórí èèyàn sí ìpalára rẹ̀.” (Oníwàásù 8:⁠9) Ohun tá à ń sọ ni pé tí èèyàn bá ń ṣàkóso ara wọn, wàhálà ló máa ń yọrí sí.

BÍ ÌJỌBA ÈÈYÀN ṢE BẸ̀RẸ̀

Nímírọ́dù dúró lọ́nà tó fi hàn pé agbéraga ẹ̀dá ni. Lọ́wọ́ ẹ̀yìn, àwọn èèyàn ń kọ́lé.

Nímírọ́dù ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà

Nímírọ́dù ni èèyàn àkọ́kọ́ tí Bíbélì sọ pé ó jẹ́ alákòóso. Ó sì ṣọ̀tẹ̀ sí àkóso Jèhófà. Látìgbà ayé Nímírọ́dù làwọn alágbára ti ń ṣi agbára wọn lò. Ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) ọdún sẹ́yìn, Ọba Sólómọ́nì sọ pé: “Mo rí omijé àwọn tí wọ́n ń ni lára, kò sí ẹni tó máa tù wọ́n nínú. Agbára wà lọ́wọ́ àwọn tó ń ni wọ́n lára.”​—Oníwàásù 4:1.

Ohun tó sì ń ṣẹlẹ̀ lónìí náà nìyẹn. Lọ́dún 2009, ìwé kan tí Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè gbé jáde sọ pé àwọn èèyàn túbọ̀ ń rí i pé ìjọba burúkú jẹ́ “ọ̀kan lára ohun tó ń fa gbogbo ìwà ibi tó ń ṣẹlẹ̀ láyé.”

ÀKÓKÒ TÓ LÁTI YANJÚ ÀWỌN ÌṢÒRO NÁÀ!

Ayé yìí nílò àwọn alákòóso àti ìjọba tó dára ju ti ìsinsìnyí lọ. Ohun tí Ẹlẹ́dàá wa sì ṣèlérí fún wa náà nìyẹn!

Gbogbo àwòrán: Ohun tí ìṣàkóso èèyàn ti fà. 1. Obìnrin ará Éṣíà kan jókòó síbì kan tó dọ̀tí, ó gbé ọmọ rẹ̀ tó ń sunkún dání. 2. Bàbá àgbàlagbà kan tó ń ṣàìsàn wà nílé ìwòsàn. 3. Àwọn sójà ń yìnbọn lójú ogun. 4. Àwọn kan ń fìbínú wọ́de, wọ́n gbé àkọlé dání. 5. Obìnrin kan àti ọmọ rẹ̀ dúró níta ilé wọn, wọ́n rí i pé ẹnì kan ti fọ́ gíláàsì ilẹ̀kùn iwájú ilé wọn. 6. Ìlú kan tí èéfín ń tú jáde látinú àwọn iléeṣẹ́ ńlá, àwọn wáyà iná sì wà káàkiri.

Èyí tó tiẹ̀ dára jù nínú ìjọba èèyàn kò lè yanjú ìṣòro aráyé

Ọlọ́run ti gbé Ìjọba kan kalẹ̀ tó máa rọ́pò gbogbo ìjọba èèyàn, “òun nìkan ló sì máa dúró títí láé.” (Dáníẹ́lì 2:44) Ìjọba yẹn ni àìmọye èèyàn ti ń gbàdúrà pé kí ó dé. (Mátíù 6:9, 10) Àmọ́ Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kọ́ ló máa darí ìjọba náà. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ti yan ẹnì kan tó máa jẹ́ Alákòóso, ẹni náà sì ti gbé ayé rí. Ta lẹni náà tí Ọlọ́run yàn?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́