ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • yb14 ojú ìwé 26-35
  • Ìròyìn Nípa Àwọn Ẹjọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìròyìn Nípa Àwọn Ẹjọ́
  • Ìwé Ọdọọdún Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Iroyin Nipa Awon Ejo
    Ìwé Ọdọọdún Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà—2015
  • Àwọn Ìṣẹ̀lẹ̀ Pàtàkì Lọ́dún tó Kọjá
    Ìwé Ọdọọdún Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà—2013
  • Ìròyìn Nípa Àwọn Ẹjọ́
    Ìwé Ọdọọdún Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà—2016
  • Ìròyìn Nípa Àwọn Ẹjọ́
    Ìwé Ọdọọdún Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà—2017
Àwọn Míì
Ìwé Ọdọọdún Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà—2014
yb14 ojú ìwé 26-35
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 27]

ÀWỌN OHUN PÀTÀKÌ TÓ ṢẸLẸ̀ LỌ́DÚN TÓ KỌJÁ

Ìròyìn Nípa Àwọn Ẹjọ́

Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù rọ àwa Kristẹni pé: “Ẹ máa fi àwọn tí ń bẹ nínú àwọn ìdè ẹ̀wọ̀n sọ́kàn bí ẹni pé a dè yín pẹ̀lú wọn.” (Héb. 13:3) Gbogbo ìgbà ni àwa ìránṣẹ́ Jèhófà máa ń rántí àwọn ará wa tí wọ́n jẹ́ olóòótọ́, a sì máa ń gbàdúrà fún “gbogbo àwọn tí ó wà ní ipò gíga; kí a lè máa bá a lọ ní gbígbé ìgbésí ayé píparọ́rọ́ àti dídákẹ́jẹ́ẹ́ pẹ̀lú fífọkànsin Ọlọ́run lẹ́kùn-ún-rẹ́rẹ́ àti ìwà àgbà.”—1 Tím. 2:1, 2; Éfé. 6:18.

Ẹ jẹ́ ká sọ̀rọ̀ nípa àwọn ẹjọ́ tó kan àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà lọ́dún tó kọjá:

Àwọn ará wa ní orílẹ̀-èdè Rọ́ṣíà “ń bá a lọ láìdábọ̀ ní kíkọ́ni àti pípolongo ìhìn rere” láìka bí Ṣọ́ọ̀ṣì Ọ́tọ́dọ́ọ̀sì ti Ilẹ̀ Rọ́ṣíà àti àwọn kan lára àwọn aláṣẹ ṣe fẹ́ fòpin sí iṣẹ́ ìwàásù wa. (Ìṣe 5:42) Àwọn aláṣẹ ilẹ̀ Rọ́ṣíà ṣì ń lo òfin kan tí kò ṣe pàtó, tó dá lórí àwọn agbawèrèmẹ́sìn láti fi gbógun ti àwọn ará wa, wọ́n sì ń fòfin de àwọn ìtẹ̀jáde wa. Bẹ́ẹ̀ sì rèé torí àwọn apániláyà ni wọ́n ṣe gbé òfin yìí kalẹ̀. Nítorí èyí, àwọn ilé ẹjọ́ nílẹ̀ Rọ́ṣíà ti ka nǹkan bí àádọ́rin [70] lára àwọn ìtẹ̀jáde wa sí ìwé tó kún fún ọ̀rọ̀ “àwọn agbawèrèmẹ́sìn,” àwọn aláṣẹ sì ti fi orúkọ àwọn ìwé yìí kún àwọn ìwé tí wọ́n fòfin dè pé ó jẹ́ ìwé àwọn agbawèrèmẹ́sìn. Torí ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn wá yìí, àwọn aláṣẹ àdúgbò bẹ̀rẹ̀ sí í lọ tú inú àwọn Gbọ̀ngàn Ìjọba àti ilé àwọn ará láti wá àwọn ìwé náà jáde. Àwọn ọlọ́pàá máa ń mú àwọn ará torí pé wọ́n ń wàásù, wọ́n á ya fọ́tò wọn, wọ́n á sì ní kí wọ́n tẹ̀ka. Ọ̀pọ̀ ìgbà ni wọ́n ń tì wọ́n mọ́lé sí àgọ́ ọlọ́pàá láti dẹ́rù bà wọ́n.

Bẹ̀rẹ̀ láti oṣù May 2013, àwọn arákùnrin àti arábìnrin mẹ́rìndínlógún [16] ní ìlú Taganrog ló ti lọ jẹ́jọ́ torí pé wọ́n ṣètò ìpàdé, wọ́n lọ sípàdé, wọ́n kópa níbẹ̀, wọ́n sì lọ sóde ẹ̀rí. Látìgbà tí ìjọba Soviet Union ti tú ká, ìgbà àkọ́kọ́ nìyí tí wọ́n á fẹ̀sùn ọ̀daràn kan àwọn ará wa torí ẹ̀sìn wọn. Láwọn ibòmíì ní ilẹ̀ Rọ́ṣíà, ìjọba ń fẹ́ kí àwọn ilé ẹjọ́ pe àwọn ìwé wa ní ìwé “àwọn agbawèrèmẹ́sìn,” kí ilé ẹjọ́ sì tún dá àwọn ará lẹ́bi pé wọ́n ń fa ìkórìíra ẹ̀sìn.

Nǹkan ò tíì rọgbọ fún àwọn ará wa lórílẹ̀-èdè Eritrea. Títí di oṣù July 2013, àwọn méjìléláàádọ́ta [52] ló wà lẹ́wọ̀n. Lára wọn ni àwọn arákùnrin mẹ́jọ tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ àádọ́rin [70] ọdún sókè àtàwọn arábìnrin mẹ́fà. Láti September 24, 1994 ni àwọn arákùnrin mẹ́ta kan ti wà lẹ́wọ̀n torí pé wọn kò lọ́wọ́ sí iṣẹ́ ológun. Orúkọ wọn ni Paulos Eyassu, Isaac Mogos àti Negede Teklemariam.

Ó lé ní ìdajì àwọn ará wa tó wà lẹ́wọ̀n tí wọ́n fi sí ọgbà ẹ̀wọ̀n Meiter tó wà ní aṣálẹ̀ ní àríwá Asmara tó jẹ́ olú ìlú orílẹ̀-èdè Eritrea. Láti oṣù October 2011 títí di August 2012, àwọn aláṣẹ fi mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n [25] lára àwọn ará wa sínú ilé kótópó kan tí wọ́n fi páànù kọ́, tí wọ́n ri ìdajì rẹ̀ mọ́lẹ̀ láti fìyà jẹ wọ́n. Nígbà ẹ̀rùn, àwọn ẹ̀ṣọ́ ọgbà ẹ̀wọ̀n náà máa ń jẹ́ kí wọ́n bọ́ síta ní ọ̀sán kí ooru má bàa mú wọn pa. Yàtọ̀ síyẹn, wọn kì í rí oúnjẹ àti omi tó pọ̀ tó, torí náà wọ́n ṣàìsàn gan-an. Bíi ti Arákùnrin Misghina Gebretinsae tó kú lọ́dún 2011, ó bani nínú jẹ́ pé Arákùnrin Yohannes Haile pẹ̀lú kú ní ẹni ọdún méjìdínláàádọ́rin [68] ní oṣù August 2012 látàrí ìfìyàjẹni tó lé kenkà yìí.

Ẹ̀rí Ọkàn Kò Jẹ́ Kí Wọ́n Ṣiṣẹ́ Ológun

Based on A gbé e ka Aísáyà 2:4 àti Jòhánù 18:36.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ ÀMÉNÍÀ

Ní November 27, 2012, Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù dá wa láre nínú ẹjọ́ tó wà láàárín Arákùnrin Khachatryan àtàwọn yòókù rẹ̀ pẹ̀lú orílẹ̀-èdè Àméníà. Ohun tó bí ọ̀rọ̀ yìí ni pé ìjọba fẹ̀sùn èké kan àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà mẹ́tàdínlógún [17] pé wọ́n jẹ́ ọ̀daràn torí wọ́n kọ̀ láti ṣe iṣẹ́ àṣesìnlú tó wà lábẹ́ ìdarí àwọn ológun. Ilé ẹjọ́ sọ pé ohun tí ìjọba ṣe kò bófin mu rárá, torí náà, ìjọba ti san owó ìtanràn àtàwọn owó yòókù tí àwọn ará wa ná lórí ẹjọ́ náà pa dà.

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù dá wa láre nínú ẹjọ́ Arákùnrin Khachatryan àti ẹjọ́ mánigbàgbé tó wà láàárín Arákùnrin Bayatyan àti orílẹ̀-èdè Àméníà títí kan àwọn ẹjọ́ míì tí wọ́n dá, ìjọba ilẹ̀ Àméníà ṣì ń fẹ̀sùn kan àwọn ọ̀dọ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà, wọ́n sì ń dá wọn lẹ́bi torí pé ẹ̀rí ọkàn wọn kò fàyè gbà wọ́n láti ṣe iṣẹ́ ológun. Àmọ́ ní June 8, 2013, ìjọba ṣe àtúnṣe sí òfin tó ń darí iṣẹ́ àṣesìnlú, èyí tó ṣeé ṣe kó yọwọ́ àwọn ológun kúrò nínú dídarí iṣẹ́ àṣesìnlú. Nígbà tó fi máa di November 12, 2013, gbogbo àwọn ará wa tó wà lẹ́wọ̀n torí pé ẹ̀rí ọkàn wọn kò gbà wọ́n láyè láti ṣiṣẹ́ ológun ni wọ́n dá sílẹ̀. Ìjọba sì ti gba àwọn ọ̀dọ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó fẹ́ ṣe iṣẹ́ àṣesìnlú láyè.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ SOUTH KOREA

Méjìlélẹ́gbẹ̀ta [602] lára àwọn ará wa ló ṣì wà lẹ́wọ̀n títí di October 31, 2013. Láti ọdún 1950, ìjọba ilẹ̀ South Korea ti rán ẹgbẹ̀rún mẹ́tàdínlógún àti márùnlélẹ́gbẹ̀ta [17,605] àwọn ará wa lẹ́wọ̀n torí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe iṣẹ́ ológun. Àpapọ̀ ọdún tí wọ́n retí kí wọ́n lò lẹ́wọ̀n jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n àti mẹ́rìnlélọ́gọ́sàn-án [34,184].

Títí di àìpẹ́ yìí, yàrá ọgbà ẹ̀wọ̀n kan náà ni ọ̀pọ̀ àwọn ará wa tí wọ́n jù sẹ́wọ̀n ń gbé pẹ̀lú àwọn ọ̀daràn, títí kan àwọn ọ̀daràn paraku. Àmọ́ ṣá, a ti rán àwọn arákùnrin kan lọ bá ọ̀gá àgbà Àjọ Tó Ń Kọ́ni Láti Jáwọ́ Nínú Ìwà Burúkú. Kí wọ́n lè bá wa sọ fún àwọn tó ń bójú tó ọgbà ẹ̀wọ̀n pé kí wọ́n kó àwọn ará wa kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹ́wọ̀n yòókù. Kíá ni àwọn aláṣẹ ọgbà ẹ̀wọ̀n kó èyí tó pọ̀ jù nínú àwọn ará wa kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọ̀daràn náà. Kódà nígbà tó fi máa di oṣù April 2013, èyí tó pọ̀ jù nínú àwọn ará wa ló jẹ́ pé àwọn arákùnrin mẹ́rin sí márùn-ún péré ni wọ́n jọ wà nínú yàrá ẹ̀wọ̀n kan náà. Báwo ni àtúnṣe yìí ṣe wá rí lára àwọn ará wa?

Arákùnrin kan sọ pé, “A ti kúrò láàárín àwọn tó lè mú ká ṣe ohun tí kò tọ́, irú bí ìṣekúṣe àti ọ̀rọ̀ èébú.” Arákùnrin míì sọ pé, “Ní báyìí, a ti ń ráyè fún ara wa ní ìṣírí a sì ń ṣe gbogbo ìpàdé márààrún lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀.”

Ní báyìí, léraléra ni wọ́n ń gbé àwọn arákùnrin mẹ́rìndínlọ́gọ́ta [56] tí wọ́n dá sílẹ̀ nínú iṣẹ́ sójà tí wọ́n sì di Ẹlẹ́rìí Jèhófà lọ sílé ẹjọ́. Wọ́n ń bu owó ìtanràn lé wọn, wọ́n sì ń fi wọ́n sí àtìmọ́lé torí pé wọn kò wá ṣe ìdálẹ́kọ̀ọ́ ológun. Torí pé ọ̀pọ̀ ìgbà ni wọ́n ń pè wọ́n fún ìdálẹ́kọ̀ọ́ yìí láti nǹkan bí ọdún mẹ́jọ báyìí, ẹjọ́ tiwọn yìí dá yàtọ̀, ó sì ṣòro gan-an láti bójú tó.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ SINGAPORE

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀pọ̀ ìgbà làwọn ará wa méjìlá tó wà ní àtìmọ́lé ní àgọ́ àwọn ológun ti béèrè pé kí wọ́n jẹ́ kí wọ́n lọ ṣe iṣẹ́ àṣesìnlú, síbẹ̀ wọ́n ṣì fi ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́ta àti oṣù mẹ́ta. Wọ́n tún fi arákùnrin míì sí ẹ̀wọ̀n ọdún kan gbáko torí pé ó kọ̀ láti gba ìdálẹ́kọ̀ọ́ tí wọ́n lè fi pè é síṣẹ́ ológun nígbà tó bá pọn dandan.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ TURKMENISTAN

Wọ́n rán àwọn arákùnrin wa mẹ́sàn-án tó kọ̀ láti wọṣẹ́ ológun lẹ́wọ̀n ọdún kan ààbọ̀ sí ọdún méjì torí ohun tí wọ́n gbà gbọ́, ọ̀pọ̀ ìgbà sì ni àwọn ẹ̀ṣọ́ ọgbà ẹ̀wọ̀n tàbí àwọn sójà máa ń lù wọ́n ní àlùbami. Tí wọ́n bá ti dá wọn sílẹ̀, àwọn aláṣẹ á tún lọ mú wọn, wọ́n á sì tún fi ẹ̀sùn kan náà kàn wọ́n, wọ́n sì máa ń fi ìyà tó ju ti tẹ́lẹ̀ lọ jẹ wọ́n ní ẹ̀wọ̀n. Agbẹjọ́rò àwọn ará wa mẹ́wàá tí wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ṣe iṣẹ́ ológun ti gbé ẹjọ́ náà lọ sí ọ̀dọ̀ Ìgbìmọ̀ Tó Ń Rí sí Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn lábẹ́ ìdarí Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè.

Ẹ̀rí Ọkàn Kò Jẹ́ Kí Wọ́n Lọ́wọ́ sí Ayẹyẹ Orílẹ̀-Èdè

A gbé e ka Dáníẹ́lì 3:16-18.

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 32]

Orílẹ̀-èdè Tanzania: Lẹ́yìn tí ilé ẹjọ́ dá àwọn ọ̀dọ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà yìí láre, wọ́n pa dà bẹ̀rẹ̀ ilé ìwé wọn

ORÍLẸ̀-ÈDÈ TANZANIA

Ní ìlú Dar es Salaam, Ilé Ẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn tó ga jù lọ lórílẹ̀-èdè Tanzania fẹnu kò pé àwọn kò fara mọ́ ohun tí àwọn aláṣẹ ilé ìwé kan ṣe bí wọ́n ṣe lé akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún kúrò níléèwé tí wọ́n sì ní kí àwọn méjìlélọ́gọ́fà [122] yòókù ṣì lọ máa gbé ilé wọn ná torí pé wọn ò kọ orin orílẹ̀-èdè. Nínú ìpinnu kan tí ilé ẹjọ́ náà gbé jáde ní July 12, 2013, ó fàyè gba ìgbàgbọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà yìí àti ẹ̀tọ́ tí wọ́n ní láti ṣe ohun tí ẹ̀rí ọkàn wọn bá fẹ́ àti ẹ̀sìn tó wù wọ́n. Bí àwọn ọ̀dọ́ yìí ṣe dúró lórí ìpinnu wọn láti máa sin Ọlọ́run jẹ́ ká borí nínú ọ̀rọ̀ yìí, èyí sì gbé orúkọ Jèhófà ga, ó tún mú ká láǹfààní láti máa bá ìjọsìn wa lọ lórílẹ̀-èdè Tanzania.

Òmìnira Láti Wàásù

A gbé e ka Ìṣe 4:19, 20.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ KAZAKHSTAN

Nínú ìkéde tí ẹ̀ka tó ń bójú tó ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn ní àgbègbè kan ṣe lẹ́yìn tí wọ́n láwọn ṣe ìwádìí kan tó jinlẹ̀, wọ́n ní àwọn kan lára ìwé wa jẹ́ ìwé àwọn agbawèrèmẹ́sìn, ó sì ń fa ìpínyà láàárín àwọn ẹlẹ́sìn àti láàárín àwùjọ. Ní April 6, 2013, àwọn ọlọ́pàá ìlú Karabalyk já wọlé nígbà tí àwọn ará ń ṣèpàdé lọ́wọ́ nínú ilé àdáni kan, wọ́n sì kó àwọn ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ lọ láìgbàṣẹ. Ní July 3, 2013, Ilé Ẹjọ́ Tó Ń Bójú Tó Ètò Ọrọ̀ Ajé ní ìlú Astana pinnu pé kí ìjọba gbẹ́sẹ̀ lé mẹ́wàá lára àwọn ìtẹ̀jáde wa, nípa bẹ́ẹ̀ wọ́n ń fimú fínlẹ̀, wọn ò sì jẹ́ ká kó àwọn ìtẹ̀jáde wa wọ̀lú. Yàtọ̀ síyẹn, láti oṣù December ọdún 2012 ni àwọn aláṣẹ ti bẹ̀rẹ̀ sí í mú àwọn ará wa tí wọ́n sì ń pè wọ́n lẹ́jọ́ pé iṣẹ́ ìwàásù tí wọ́n ń ṣe kò bá òfin mu. Ní March 28, 2013, àjọ tó ń bójú tó ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn pàṣẹ pé kí àwọn tó ń bójú tó ẹ̀sìn àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní àgbègbè yẹn sọ fún gbogbo àwọn ará tó wà ní orílẹ̀-èdè Kazakhstan pé kò bófin mu kí wọ́n máa wàásù láwọn ibòmíì yàtọ̀ sí àwọn ilé tí ìjọba fọwọ́ sí pé kí wọ́n ti máa jọ́sìn. Nígbà tó fi máa di oṣù July 2013, mọ́kànlélógún [21] lára àwọn ará wa ni ìjọba ti pè lẹ́jọ́ lórí ọ̀rọ̀ yìí.

Òmìnira Láti Pé Jọ Ká sì Máa Bára Kẹ́gbẹ́

A gbé e ka Hébérù 10:24, 25.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ AZERBAIJAN

Ní January 2010, ìgbìmọ̀ tí ìjọba yàn láti máa bójú tó ohun tí àjọ ẹ̀sìn kọ̀ọ̀kan ń ṣe kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ kí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tún orúkọ wọn fi sílẹ̀ torí pé wọ́n ní àwọn rí àwọn àṣìṣe kan nínú ìwé tí wọ́n fẹ́ fi forúkọ sílẹ̀ lábẹ́ òfin. Láìka pé a ti ṣakitiyan lọ́pọ̀ ìgbà ká lè ṣàtúnṣe àwọn nǹkan tí wọ́n ní àwọn rí yìí, ìjọba ṣì ta kú pé àwọn ò ní jẹ́ ká tún orúkọ wa fi sílẹ̀. Ní July 31, 2012, àwọn ará wa gbé ẹjọ́ náà lọ sí Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù, wọ́n sọ pé ìjọba ti fi ẹ̀tọ́ tá a ní láti ṣe ẹ̀sìn dù wá torí pé wọ́n kọ̀ láti jẹ́ ká tún orúkọ ẹ̀sìn wa fi sílẹ̀ lábẹ́ òfin láìsí ìdí kankan tó bófin mu. Tí a ò bá sì tún orúkọ ẹ̀sìn wa fi sílẹ̀, àwọn ara wa kò ní lè ní òmìnira ẹ̀sìn.

Ẹ̀tọ́ Tá A Ní Láti Dáàbò Bo Ara Wa àti Ohun Ìní Wa

A gbé e ka Fílípì 1:7.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ UKRAINE

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń gbádùn àǹfààní tí wọ́n ní láti máa jọ́sìn lórílẹ̀-èdè Ukraine, àwọn èèyàn máa ń lù wọ́n, wọ́n máa ń dáná sun ilé àtàwọn ohun ìní wọn, kódà wọ́n tún máa ń ba nǹkan jẹ́ láwọn Gbọ̀ngàn Ìjọba. Ó dunni pé àwọn agbófinró kì í ṣe ìwádìí tó yẹ lórí àwọn ọ̀ràn yìí, wọn kì í sì í fìyà jẹ àwọn tó ń fa gbogbo wàhálà yìí. Abájọ tí àwọn alátakò yìí fi ń wò ó pé àwọn lè tẹra mọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ káwọn sì mú un jẹ. Èyí ti mú kí àwọn nǹkan tí kò bófin mu tí wọ́n ṣe sí àwọn ará lọ́dún 2012 àti 2013 túbọ̀ pọ̀ sí i. Lọ́dún 2010, ìgbà márùn-ún ló wà lákọsílẹ̀ pé wọ́n ba nǹkan àwọn ará jẹ́ tàbí kí wọ́n dáná sun ún, àmọ́ ó tó ìgbà mẹ́ẹ̀ẹ́dógún tírú nǹkan bẹ́ẹ̀ wáyé lọ́dún 2011. Nígbà tó fi máa di ọdún 2012, àádọ́ta [50] ìgbà ló tún wáyé, nígbà tó sì jẹ́ pé lẹ́nu oṣù márùn-ún àkọ́kọ́ lọ́dún 2013, ó tó ìgbà mẹ́tàlélógún [23] tírú ìṣẹ̀lẹ̀ láabi yìí tún wáyé. Ẹ̀ka ọ́fíìsì wa ti ń ṣiṣẹ́ lórí bí wọ́n á ṣe mú ẹjọ́ yìí lọ sọ́dọ̀ Ìgbìmọ̀ Tó Ń Rí sí Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn lábẹ́ ìdarí Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè.

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 28]

Orílẹ̀-èdè Ukraine: Àwọn kan ba Gbọ̀ngàn Ìjọba yìí jẹ́ wọ́n sì dáná sun ún, àmọ́ àwọn ará wa ti ń múra bí wọ́n ṣe máa tún un ṣe

Ẹ̀tọ́ Tá A Ní Láti Dúró Lórí Ìpinnu Wa

A gbé e ka Ìṣe 5:29 àti Ìṣe 15:28, 29.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ AJẸNTÍNÀ

Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 2012, ọ̀pọ̀ ọta ìbọn ba Arákùnrin Pablo Albarracini lára nígbà tí àwọn adigunjalè kan ṣọṣẹ́ nítòsí ibi tó dúró sí, kódà ó ti dákú lọ nígbà tí wọ́n fi máa gbé e dé ilé ìwòsàn. Àmọ́ ó ti buwọ́ lu káàdì tá a fi ń fa àṣẹ ọ̀rọ̀ ìtọ́jú lé aṣojú ẹni lọ́wọ́ pé òun kò fẹ́ ìtọ́jú tó bá la lílo àwọn èròjà ẹ̀jẹ̀ lọ. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn dókítà fara mọ́ ìpinnu tó ṣe yìí, ẹnì kan tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà lára àwọn mọ̀lẹ́bí arákùnrin náà kò fara mọ́ ọn, ṣe ló fẹ́ lọ gba àṣẹ nílé ẹjọ́ pé kí wọ́n fi dandan fa ẹ̀jẹ̀ sí Arákùnrin Albarracini lára, ó ní ó máa kú tí kò bá gba ẹ̀jẹ̀. Àmọ́ Ilé Ẹjọ́ Gíga Jù Lọ lórílẹ̀-èdè Ajẹntínà dá Arákùnrin Albarracini láre pé ó lẹ́tọ̀ọ́ láti sọ bó ṣe yẹ kí wọ́n tọ́jú òun kódà tí kò bá tiẹ̀ mọ nǹkan kan mọ́. Kò gba ẹ̀jẹ̀ sára, àmọ́ ara rẹ̀ yá gágá. Ó dúpẹ́ pé Jèhófà jẹ́ kí òun lè dúró lórí ìpinnu òun nínú ọ̀rọ̀ pàtàkì yìí.

Wọ́n Ṣe Ẹ̀tanú sí Wọn Nítorí Ẹ̀sìn Wọn

A gbé e ka Lúùkù 21:12-17.

ORÍLẸ̀-ÈDÈ KYRGYZSTAN

Ní April 16, 2013, ilé ẹjọ́ dá àwọn ará wa láre ní ìlú Toktogul. Ẹ̀ẹ̀mejì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ làwọn ará ìlú náà ba Gbọ̀ngàn Ìjọba wa jẹ́. Ilé ẹjọ́ dá àwọn tó hùwà láabi náà lẹ́bi, ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n san owó ìtanràn. Ẹjọ́ àwọn tó kọ́kọ́ dá wàhálà ọ̀hún sílẹ̀ ṣì ń lọ lọ́wọ́, a sì retí pé èyí máa jẹ́ kí àwọn ìṣòro tá a ní níbẹ̀ yanjú. Ní báyìí ná, àwọn ìjọ tó wà níbẹ̀ máa tún Gbọ̀ngàn Ìjọba náà kọ́.

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 34]

Orílẹ̀-èdè Kyrgyzstan: Ẹ̀ẹ̀mejì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ làwọn ará ìlú ba Gbọ̀ngàn Ìjọba yìí jẹ́

Ilé Ẹjọ́ Dá Wa Láre Nínú Àwọn Ẹjọ́ Mánigbàgbé

  1. Ọ̀rọ̀ tó jẹ yọ: Ǹjẹ́ ó dìgbà tí ẹ̀sìn kan bá gba àṣẹ kó tó lè ṣe àwọn àpéjọ àti ìpàdé?

    Ìdájọ́: Ní December 5, 2012, Ilé Ẹjọ́ Ìjọba Ilẹ̀ Rọ́ṣíà fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé òfin ilẹ̀ Rọ́ṣíà gba àwọn èèyàn láyè láti ṣe ẹ̀sìn tó wù wọ́n, ó sì dá àwọn ará wa láre pé wọ́n ní ẹ̀tọ́ láti máa ṣe àwọn ìpàdé ìjọ láì kọ́kọ́ sọ fún ìjọba tàbí kí wọ́n gba àṣẹ.

  2. Ọ̀rọ̀ tó jẹ yọ: Ǹjẹ́ àwọn ará ìlú ní ẹ̀tọ́ láti ṣe àkọsílẹ̀ ìtọ́jú tí wọ́n ṣe nílé ìwòsàn ní àṣírí? Ohun tó ṣẹlẹ̀: Lọ́dún 2007, igbákejì agbẹjọ́rò ìjọba ní ìlú St. Petersburg, lórílẹ̀-èdè Rọ́ṣíà, pa àṣẹ fún gbogbo ilé ìwòsàn tó wà ní ìlú náà pé kí wọ́n fi gbogbo àkọsílẹ̀ nípa àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tí kò gba ẹ̀jẹ̀ sára ránṣẹ́ sí ọ́fíìsì agbẹjọ́rò ìjọba láìjẹ́ pé àwọn tó gba ìtọ́jú mọ̀ nípa rẹ̀. Nígbà tí àwọn ilé ẹjọ́ ilẹ̀ Rọ́ṣíà kọ̀ láti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé àwọn tó gba ìtọ́jú ní ẹ̀tọ́ láti ṣe àkọsílẹ̀ ìtọ́jú tí wọ́n ṣe nílé ìwòsàn ní àṣírí, a gbé ẹjọ́ náà lọ sí Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù.

    Ìdájọ́: Ní June 6, 2013, Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù dá agbẹjọ́rò náà lẹ́bi pé ó ti kọjá àyè rẹ̀ àti pé “kó sì ẹ̀rí tó lẹ́sẹ̀ nílẹ̀” pé àwọn lọ́gàá-lọ́gàá lẹ́nu iṣẹ́ ìjọba ní ẹ̀tọ́ láti rí àkọsílẹ̀ ìtọ́jú àwọn èèyàn. Ìdájọ́ yìí túbọ̀ fẹsẹ̀ múlẹ̀ ní October 7, nígbà tí Ìgbìmọ̀ Tó Ga Jù Lọ ní Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù kọ̀ jálẹ̀ láti gbọ́ ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn tí ìjọba ilẹ̀ Rọ́ṣíà gbé lọ sọ́dọ̀ wọn.—Ẹjọ́ tó wà láàárín Arákùnrin Avilkina àtàwọn yòókù pẹ̀lú ilẹ̀ Rọ́ṣíà.

Ìròyìn Nípa Àwọn Ẹjọ́ Tá A Mẹ́nu Bà Nínú Ìwé Ọdọọdún Tó Kọjá

Ìjọba ilẹ̀ Faransé ti gbà pé àwọn máa dá owó orí tí wọ́n fi èrú gbà lọ́wọ́ wa pa dà bí Ilé Ẹjọ́ Ẹ̀tọ́ Ọmọnìyàn ti Ilẹ̀ Yúróòpù ṣe pa á láṣẹ ní July 5, 2012. Wọ́n ti dá owó tí wọ́n fipá gbà lọ́wọ́ wa pa dà, títí kan èlé orí owó náà àti owó tí a ná sórí ẹjọ́ náà, wọ́n sì ti gbẹ́sẹ̀ kúrò lórí gbogbo dúkìá tó jẹ́ ti ẹ̀ka ọ́fíìsì.—Ìwé Ọdọọdún 2013, ojú ìwé 34.

Wọ́n ṣì ń ṣe àtakò sí àwọn ará wa káàkiri orílẹ̀-èdè Íńdíà. Àmọ́ wọn ò fi wọ́n sí àtìmọ́lé, wọn kò sì fi ẹ̀sùn èké kàn wọ́n mọ́ bíi ti tẹ́lẹ̀. Nǹkan bí ogún [20] ẹjọ́ la ti gbé lọ sílé ẹjọ́ báyìí kí àwọn tó hùwà àìtọ́ sí àwọn ará wa lè kọwọ́ ọmọ wọn bọ aṣọ.—Ìwé Ọdọọdún 2013, ojú ìwé 35.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́