ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ijwbq àpilẹ̀kọ 114
  • Ṣé “Ẹ̀ṣẹ̀ Méje Tó La Ikú Lọ” Wà Lóòótọ́?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣé “Ẹ̀ṣẹ̀ Méje Tó La Ikú Lọ” Wà Lóòótọ́?
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun tí Bíbélì sọ
  • Kí Ni Ẹ̀ṣẹ̀?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ọlọ́run Tó “Ṣe Tán Láti Dárí Jini”
    Sún Mọ́ Jèhófà
  • Ṣé Ọlọ́run Béèrè Pé Ká Máa Jẹ́wọ́ Ẹ̀ṣẹ̀?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Aráyé Kò Ka Ẹ̀ṣẹ̀ Sí Nǹkan Kan Mọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
Àwọn Míì
Ohun Tí Bíbélì Sọ
ijwbq àpilẹ̀kọ 114
Ọkùnrin kan tí inú ẹ̀ bà jẹ́

Ṣé “Ẹ̀ṣẹ̀ Méje Tó La Ikú Lọ” Wà Lóòótọ́?

Ohun tí Bíbélì sọ

Bíbélì ò dárúkọ “ẹ̀ṣẹ̀ méje tó la ikú lọ.” Àmọ́ ó sọ pé ẹni tó bá ń dẹ́ṣẹ̀ tó burú jáì ò ní rígbàlà. Bí àpẹẹrẹ, Bíbélì pe àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tó burú jáì yìí, bí àgbèrè, ìbọ̀rìṣà, ìbẹ́mìílò, ìrufùfù ìbínú àti mímu àmuyíràá ní “àwọn iṣẹ́ ti ara.” Ó wá sọ pé: “Àwọn tí ń fi irúfẹ́ nǹkan báwọ̀nyí ṣe ìwà hù kì yóò jogún ìjọba Ọlọ́run.”​—Gálátíà 5:19-​21.a

Ṣebí Bíbélì mẹ́nu ba ‘ohun méje tí ó ṣe ìríra fún Olúwa’?

Òótọ́ ni. Bíbélì Mímọ́ túmọ̀ Òwe 6:16 lọ́nà yìí: “Ohun mẹ́fà ni Olúwa kórìíra: nítòótọ́, méje ni ó ṣe ìríra fún ọkàn rẹ̀.” Àmọ́ kò túmọ̀ sí pé àwọn ohun tí Òwe 6:17-​19 mẹ́nu bà nìkan ló burú lójú Ọlọ́run. Kàkà bẹ́ẹ̀, àwọn ohun tó mẹ́nu bà kó onírúurú ẹ̀ṣẹ̀ pọ̀, títí kan ẹ̀ṣẹ̀ tó jẹ mọ́ èrò, ọ̀rọ̀ àti ìṣe.b

Kí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ náà, “ẹ̀ṣẹ̀ tó la ikú lọ”?

Àwọn ìtúmọ̀ Bíbélì kan lo ọ̀rọ̀ yìí ní 1 Jòhánù 5:16. Bí àpẹẹrẹ, Bibeli Ìròyìn Ayọ̀ sọ pé: “Ẹ̀ṣẹ̀ mìíràn wà tí ó la ti ikú lọ.” Ọ̀rọ̀ náà ‘ẹ̀ṣẹ̀ tí ó la ikú lọ’ tún lè túmọ̀ sí ‘ẹ̀ṣẹ̀ tí ń fa ikú wá báni.’ Ìyàtọ̀ wo ló wà láàárín ‘ẹ̀ṣẹ̀ tí ń fa ikú wá báni’ àti ‘ẹ̀ṣẹ̀ tí kì í fa ikú wá báni’?​—1 Jòhánù 5:16.

Bíbélì jẹ́ kó ṣe kedere pé gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ló ń yọrí sí ikú. Àmọ́ ẹbọ ìràpadà Jésù Kristi lè gbà wá lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú. (Róòmù 5:12; 6:23) Torí náà, ẹbọ ìràpadà Kristi ò lè ṣe ètùtù fún ‘ẹ̀ṣẹ̀ tí ń fa ikú wá báni.’ Téèyàn bá dá irú ẹ̀ṣẹ̀ yìí, ohun tó túmọ̀ sí ni pé ẹni náà ń mọ̀ọ́mọ̀ dẹ́ṣẹ̀, kò sì ṣe tán láti yíwà pa dà. Bíbélì tún pe irú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ní ẹ̀ṣẹ̀ tí “a kì yóò dárí [rẹ̀] jini.”​—Mátíù 12:31; Lúùkù 12:10.

Ibo ni wọ́n ti rí ẹ̀ṣẹ̀ méje tó la ikú lọ?

Láyé àtijọ́, àwọn ìwà burúkú mẹ́jọ kan ni wọ́n fi pilẹ̀ “ẹ̀ṣẹ̀ méje tó la ikú lọ.” Ọgọ́rùn-ún ọdún kẹrin ni ọ̀gbẹ́ni ẹlẹ́sìn kan tó ń jẹ́ Evagrius Ponticus dá ọ̀rọ̀ yẹn sílẹ̀, iṣẹ́ tí ọ̀gbẹ́ni yẹn ṣe ló mú kí ọkùnrin kan tó ń jẹ́ John Cassian tó jẹ́jẹ̀ẹ́ ìnìkàngbé, tó sì gba ẹ̀sìn kanrí kọ àwọn ìwé tó kọ. Ní ọgọ́rùn-ún ọdún kẹfà, Póòpù Gregory Kìíní yí ohun mẹ́jọ tí ọ̀gbẹ́ni Cassian pè ní ìwà burúkú pa dà sí ẹ̀ṣẹ̀ méje tó la ikú lọ tàbí ẹ̀ṣẹ̀ tó wúwo jù, èyí tí Ìjọ Kátólíìkì fi kọ́ni. Àwọn ni: ìgbéraga, ìwọra, ìṣekúṣe, ìlara, wọ̀bìà, ìbínú àti ìmẹ́lẹ́. Ọ̀gbẹ́ni Gregory ka àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tàbí ẹ̀ṣẹ̀ tó wúwo jù torí ó gbà pé àwọn ló pilẹ̀ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yòókù.

a Òótọ́ ni pé ìwé Gálátíà 5:19-​21 mẹ́nu ba àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (15) tó burú jáì, àmọ́ ìyẹn ò túmọ̀ sí pé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yẹn nìkan ló burú, torí lẹ́yìn tí Bíbélì mẹ́nu bà wọ́n, ó fi kún un pé “àti nǹkan báwọ̀nyí.” Torí náà, ó yẹ kí ẹni tó ń kà á fi òye mọ àwọn ohun tí Bíbélì ò tò sínú ẹsẹ yẹn, èyí tó pè ní “nǹkan báwọ̀nyí.”

b Àpẹẹrẹ àkànlò èdè Hébérù kan ló wà nínú ìwé Òwe 6:16, tí wọ́n ti lo nọ́ńbà méjì tó yàtọ̀ síra láti fi tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀. Ìwé Mímọ́ sábà máa ń lo irú àkànlò èdè yìí.​—Jóòbù 5:19; Òwe 30:15, 18, 21.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́