Àfikún Àlàyé
^ [1] (ìpínrọ̀ 14) Ọ̀pọ̀ nǹkan tó ṣẹlẹ̀ sáwọn Júù tó lọ sígbèkún fún àádọ́rin [70] ọdún jọra pẹ̀lú ohun tó ṣẹlẹ̀ sáwọn Kristẹni lẹ́yìn táwọn àpọ́sítélì kú tí ìpẹ̀yìndà sì bẹ̀rẹ̀. Àmọ́, kò jọ pé lílọ táwọn Júù lọ sígbèkùn jẹ́ àpẹẹrẹ ohun tó ṣẹlẹ̀ sáwọn Kristẹni. Kókó kan ni pé, ọdún tí àwùjọ kọ̀ọ̀kan fi wà nígbèkùn yàtọ̀ síra. Torí náà, kò sídìí tó fi yẹ ká máa wá kúlẹ̀kúlẹ̀ bí ìgbèkùn àwọn Kristẹni ṣe jọra pẹ̀lú tàwọn Júù, bí ẹni pé ohun tó ṣẹlẹ̀ sáwọn Júù ní láti bá ohun tó ṣẹlẹ̀ sáwọn ẹni àmì òróró mu láwọn ọdún yẹn títí di ọdún 1919.