Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìjíròrò wa dá lórí ohun tí Bíbélì pè ní por·neiʹa, ìyẹn àgbèrè. (1 Kọ́ríńtì 6:9; fi wé Léfítíkù 18:6-22.) Èyí sì ní nínú, gbogbo ohun tó jẹ mọ́ ìṣekúṣe. Lára àwọn ìwà burúkú míì ni, kẹ́nì kan máa fi ìhòòhò rẹ̀ han ọmọdé, kó máa wo ìhòòhò ọmọdé tàbí kó máa fi àwòrán oníhòòhò han ọmọdé. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ìwà yìí kì í ṣe por·neiʹa ní tààràtà, síbẹ̀ wọ́n máa ń ṣàkóbá fún ọmọ tí wọ́n bá ṣe irú ẹ̀ sí.