Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Wíwẹ èébú síni lára lè jẹ́ ìgbésẹ̀ ìṣáájú sí ìwà ipá nínú ilé. (Fi wé Ẹ́kísódù 21:18.) Ẹnì kan tí ń gba àwọn obìnrin tí a fìyà jẹ nímọ̀ràn sọ pé: “Gbogbo obìnrin tí ń wá fún àṣẹ ìdáàbòbò lòdì sí ìluni, ìgúnni lọ́bẹ, tàbí fífúnni lọ́rùn, tí ń fi ìwàláàyè sínú ewu, ló ti ní ìtàn gígùn ti ìfìyàjẹni tí kò ṣeé fojú rí, tí ó kún fún ìpalára ní àfikún.”