Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
d Èrò orí ìṣẹ̀dá wé mọ́ ìgbàgbọ́ pé a ṣẹ̀dá ilẹ̀ ayé ní àwọn ọjọ́ oníwákàtí 24 mẹ́fà, tàbí nínú àwọn ọ̀ràn kan, pé a ṣẹ̀dá ilẹ̀ ayé ní kìkì nǹkan bí ẹgbàarùn-ún ọdún sẹ́yìn. Nígbà tí ó jẹ́ pé Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà gbà gbọ́ nínú ìṣẹ̀dá, wọn kì í ṣe elérò orí ìṣẹ̀dá. Wọ́n gbà gbọ́ pé àkọsílẹ̀ ìròyìn inú ìwé Jẹ́nẹ́sísì nínú Bíbélì fàyè gbà á pé ilẹ̀ ayé ti lè wà fún àràádọ́ta ọ̀kẹ́ ọdún.