Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Lọ́nà wíwọnilọ́kàn, àwọn alágbàwí ààbò ẹ̀dá tí ń lépa ìdáàbòbò iye tí ó bá lè ṣeé ṣe lára àwọn irú ọ̀wọ́ tí a wu léwu ṣàpèjúwe ìlànà ìwà híhù wọn bí “ìlànà Nóà” nítorí pé Nóà la fún láṣẹ láti kó “gbogbo ẹ̀dá alààyè ti gbogbo onírúurú ẹran” sínú áàkì. (Jẹ́nẹ́sísì 6:19) Onímọ̀ nípa ohun alààyè náà, David Ehrenfeld, sọ pé: “Wíwà tí [àwọn irú ọ̀wọ́] ti wà tipẹ́tipẹ́ nínú ìṣẹ̀dá gbọ́dọ̀ ní ẹ̀tọ́ tí kò ṣeé ṣiyèméjì nípa rẹ̀ náà, láti máa wà nìṣó, nínú.”