Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ilé-Ìṣọ́nà, October 15, 1991, ojú ìwé 31, pèsè àwọn ìtọ́sọ́nà wọ̀nyí pé: “Kristẹni ojulowo kan nilati ṣagbeyẹwo pe: Njẹ titẹle aṣa kan ha le fihan awọn ẹlomiran pe mo ti tẹwọgba awọn igbagbọ ati aṣa ti kò bá iwe mimọ mu bi? Saa akoko ati ibi ti a wà le nipa lori idahun naa. Aṣa kan (tabi iṣẹ́ ọnà) ti le ni itumọ isin eke ninu ni ẹgbẹẹgbẹrun ọdun sẹhin tabi ti le ni iru rẹ̀ lonii ni ilẹ jijinna réré kan. Ṣugbọn lai lọ sinu iṣayẹwo ti o gba akoko, beere lọwọ araa rẹ pe: ‘Ki ni oju iwoye ti o wọpọ nibi ti mo ngbe?’—Fiwe 1 Kọrinti 10:25-29.”