Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Lóòótọ́, nínú àwọn ọ̀ràn kan tó burú jáì, ìdí pàtàkì lè wà tí yóò mú kí ọkọ àti aya pínyà. (1 Kọ́ríńtì 7:10, 11) Ní àfikún sí i, Bíbélì gba ìkọ̀sílẹ̀ láyè lórí ìpìlẹ̀ àgbèrè. (Mátíù 19:9) Yálà ó yẹ kéèyàn kọ ẹnì kejì rẹ̀ tó jẹ́ aláìṣòótọ́ sílẹ̀ tàbí kò yẹ jẹ́ ìpinnu ara ẹni, kò sì yẹ kí àwọn ẹlòmíràn máa ti ẹni tó ṣe olóòótọ́ náà láti pinnu yálà láti kọ ẹnì kejì rẹ̀ sílẹ̀ tàbí kó má kọ̀ ọ́.—Wo ìwé Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé, ojú ìwé 158 sí 161, tí Watchtower Bible and Tract Society of New York, Inc., ṣe.