Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Irú ojú tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi wo iṣẹ́ wíwàásù làwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà náà fi wò ó, pé ohun tó pọndandan ni fáwọn Kristẹni tòótọ́. Pọ́ọ̀lù sọ pé: “Wàyí o, bí mo bá ń polongo ìhìn rere, kì í ṣe ìdí kankan fún mi láti ṣògo, nítorí àìgbọ́dọ̀máṣe wà lórí mi.” (1 Kọ́ríńtì 9:16) Síbẹ̀síbẹ̀, iṣẹ́ ìwàásù wọn jẹ́ èyí tí wọ́n yọ̀ǹda ara wọn tinútinú láti ṣe nítorí pé fúnra wọn ni wọ́n yàn láti di ọmọ ẹ̀yìn Kristi, wọ́n sì mọ̀ dájú pé ẹrù iṣẹ́ wà nídìí àǹfààní yẹn.