Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Bíbélì sọ nípa “Ha-Mágẹ́dọ́nì,” èyí tá a tún mọ̀ sí “ogun ọjọ́ ńlá Ọlọ́run Olódùmarè.” Kì í ṣe ogun tí ẹ̀dá èèyàn ń jà ni èyí tọ́ka sí o, àmọ́ ó ń tọ́ka sí bí Ọlọ́run ṣe máa ṣa àwọn èèyàn búburú sọ́tọ̀ tá á sì pa wọ́n run. Nítorí náà, èèyàn ò lè fi ti Ha-Mágẹ́dọ́nì kẹ́wọ́ pé òun ló mú kí ogun tí wọ́n ń jà lóde òní tọ̀nà tàbí kéèyàn máa rò pé Ọlọ́run fọwọ́ sí àwọn ogun náà.—Ìṣípayá 16:14, 16; 21:8.