Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ní ọ̀rúndún kìíní, àwọn èèyàn sábà máa ń jẹun ní àjẹkì nígbà táwọn ará Róòmù bá ń ṣe àríyá tó hẹ̀rẹ̀ǹtẹ̀. Èyí ló mú kí a pàṣẹ fàwọn Kristẹni láti má ṣe gba oúnjẹ tàbí ohunkóhun mìíràn tó bá fara jọ ọ́ láyè láti sọ wọ́n dẹrú.—Róòmù 6:16; 1 Kọ́ríńtì 6:12, 13; Títù 2:3.