Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó dùn mọ́ni pé Bíbélì rán àwọn Kristẹni létí pé ohun tó ń jáde lẹ́nu wọn kò ṣeé yà kúrò lára ìjọsìn wọn. Ó sọ pé: “Bí ọkùnrin èyíkéyìí lójú ara rẹ̀ bá dà bí olùjọsìn ní irú ọ̀nà kan, síbẹ̀ tí kò kó ahọ́n rẹ̀ níjàánu, ṣùgbọ́n tí ó ń bá a lọ ní títan ọkàn-àyà ara rẹ̀ jẹ, ọ̀nà ìjọsìn ọkùnrin yìí jẹ́ ìmúlẹ̀mófo.”—Jákọ́bù 1:26.