Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Gbogbo àwọn tí òbí bá yan ọkọ tàbí ìyàwó fún kọ́ ni ìgbéyàwó wọn máa ń níṣòro o. Bí àpẹẹrẹ, nínú Bíbélì, àwọn òbí ló ṣètò ìgbéyàwó Ísákì àti Rèbékà, Ísákì sì “kó sínú ìfẹ́ fún” un. (Jẹ́nẹ́sísì 24:67) Kí wá la rí kọ́ nínú ìyẹn? Má tètè máa rọ́ àwọn àṣà ìbílẹ̀ tì sẹ́gbẹ̀ẹ́ bí wọn ò bá ti ta ko òfin Ọlọ́run.—Ìṣe 5:29.