Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ohun tí wọ́n sábà máa ń pè ní ère ìsìn ni àwòrán tàbí àmì kan táwọn ẹlẹ́sìn kan máa ń jọ́sìn. Bí àpẹẹrẹ, ní Ṣọ́ọ̀ṣì Ọ́tọ́dọ́ọ̀sì ti Ìlà Oòrùn, wọ́n ní àwọn àwòrán tàbí àmì tó dúró fún Kristi; àwọn míì sì wà tó dúró fún Mẹ́talọ́kan, àwọn “ẹni mímọ́,” tàbí àwọn áńgẹ́lì, tó fi mọ́ àwòrán tàbí àmì tó dúró fún Màríà, ìyá Jésù, gẹ́gẹ́ bá a ṣe sọ lókè. Ọ̀wọ̀ tí àìmọye èèyàn ní fún irú àwòrán tàbí àmì bẹ́ẹ̀ kò fi bẹ́ẹ̀ yàtọ̀ sí ojú tí ọ̀pọ̀ èèyàn fi ń wo àwọn ère tàbí àwòrán tí wọ́n ń lò nínú ìjọsìn. Àwọn ìsìn kan tí wọn kò pe ara wọn ní Kristẹni náà ní irú ìgbàgbọ́ bẹ́ẹ̀ nínú ère àti àwòrán àwọn òrìṣà tí wọ́n ń bọ.