Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan, o lè gbìyànjú kó o kọ bó ṣe ń ṣe ẹ́ sílẹ̀. Èèyàn tó mọ bí nǹkan ṣe ń rí lára làwọn òǹkọ̀wé Sáàmù tó wà nínú Bíbélì, ìyẹn ni wọ́n ṣe mọ àwọn ọ̀rọ̀ tó yẹ láti lò nígbà tí wọ́n bá ń sọ̀rọ̀ nípa àbámọ̀, ìbínú, ìjákulẹ̀ àti ìbànújẹ́. Bí àpẹẹrẹ, o ò ṣe ṣàyẹ̀wò Sáàmù orí 6, 13, 42, 55, àti 69.