Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àwọn kan sọ pé kì í ṣe ọdún gidi làwọn ọdún tí Bíbélì ń mẹ́nu kàn yẹn, oṣù ni wọn. Àmọ́, ẹsẹ Ìwé Mímọ́ náà sọ pé Ápákíṣádì bí Ṣélà nígbà tó pé ọmọ ọdún márùndínlógójì. Tá a bá sọ pé oṣù márùndínlógójì ni Bíbélì ń sọ níbẹ̀ yẹn, á jẹ́ pé Ápákíṣádì ti di bàbá ọmọ kó tó pé ọmọ ọdún mẹ́ta, ó dájú pé ìyẹn ò lè ṣeé ṣe. Yàtọ̀ síyẹn, àwọn orí tó ṣáájú nínú ìwé Jẹ́nẹ́sísì lo oòrùn àti òṣùpá láti fi ìyàtọ̀ kedere hàn láàárín bí ọdún ṣe máa ń yí po àti bí oṣù ṣe máa ń yí po.—Jẹ́nẹ́sísì 1:14-16; 7:11.