Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àwọn abọ̀rìṣà ló ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbí méjì péré tá a lè rí kà nínú Ìwé Mímọ́, ọ̀rọ̀ tí Ìwé Mímọ́ sọ nípa wọn ò sì dáa. (Jẹ́nẹ́sísì 40:20-22; Máàkù 6:21-28) Àmọ́ ṣá o, Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ò sọ pé ká má máa fáwọn èèyàn lẹ́bùn o. Ohun tó ṣe pàtàkì ni pé kí ẹ̀bùn náà ti ọkàn wá, kó má ṣe jẹ́ torí pé a fẹ́ ṣe ohun tẹ́gbẹ́ ń ṣe tàbí pé à ń bẹ̀rù ohun táwọn èèyàn máa sọ.—Òwe 11:25; Lúùkù 6:38; Ìṣe 20:35; 2 Kọ́ríńtì 9:7.