Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Kíyè sí i pé a ò lè lo ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yìí láti fi hàn pé iná ń bẹ nínú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀ náà, bí ẹni pé ọ̀gbun àìnísàlẹ̀ náà jẹ́ hẹ́ẹ̀lì oníná. Jòhánù sọ pé òun rí èéfín tó nípọn “bí,” tàbí tó dà bí, èéfín ìléru ńlá. (Ìṣípayá 9:2) Kò sọ pé òun ráwọn ọwọ́ iná gidi nínú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀ náà.