Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Láìdà bí àwọn eéṣú náà, agbo àwọn agẹṣinjagun tí Jòhánù rí yìí ò dé “ohun tí ó rí bí adé tí ó dà bí wúrà.” (Ìṣípayá 9:7) Èyí bá òtítọ́ náà mu pé ogunlọ́gọ̀ ńlá, tó pọ̀ jù nínú agbo agẹṣinjagun náà lónìí, kò nírètí láti jọba nínú Ìjọba ọ̀run ti Ọlọ́run.