Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b “Ọ̀gbun àìnísàlẹ̀” (Gíríìkì, aʹbys·sos; Hébérù, tehohmʹ) lọ́nà ìṣàpẹẹrẹ, túmọ̀ sí ibi àìlèṣiṣẹ́mọ́. (Wo Ìṣípayá 9:2.) Àmọ́ ṣá o, ní ìtumọ̀ ṣangiliti, ó tún lè tọ́ka sí alagbalúgbú òkun. Wọ́n sábà máa ń túmọ̀ ọ̀rọ̀ Hébérù yìí sí “ibú omi.” (Sáàmù 71:20; 106:9; Jónà 2:5) Nípa báyìí, a lè sọ pé “ẹranko ẹhànnà tó gòkè wá látinú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀” jẹ́ ọ̀kan náà pẹ̀lú “ẹranko ẹhànnà kan tó ń gòkè bọ̀ láti inú òkun.”—Ìṣípayá 11:7; 13:1.