Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nínú ìwé Essay on the Development of Christian Doctrine, èyí tí kádínà Roman Kátólíìkì ti ọ̀rúndún kọkàndínlógún náà John Henry Newman kọ, ó fi hàn pé kì í ṣe inú ẹ̀sìn Kristẹni ni ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́ àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì apẹ̀yìndà, àwọn ayẹyẹ wọn àtàwọn àṣà tí wọ́n ń tẹ̀ lé ti wá. Ó wá ṣàlàyé pé: “Àtọ̀dọ̀ àwọn olórìṣà la ti kọ́ ìlò àwọn tẹ́ńpìlì tí a sì ya ìwọ̀nyí sí mímọ́ fún àwọn ẹni mímọ́ kan ní pàtó, tí a sì tún ń fi àwọn ẹ̀ka igi ṣe wọ́n lọ́ṣọ̀ọ́ nígbà míì; tùràrí, fìtílà, àti àbẹ́là; ẹ̀jẹ́ sísan lẹ́yìn téèyàn bá ti rí ìwòsàn gbà; omi mímọ́; ilé ààbò; àwọn ọjọ́ àti àsìkò mímọ́, ìlò kàlẹ́ńdà, ìtòlọ́wọ̀ọ̀wọ́rìn, àti ìsúre lórí pápá; aṣọ oyè àlùfáà, ìfárí oyè, òrùka ìgbéyàwó, yíyíjú sí Ìlà Oòrùn, ère táwọn Kristẹni wá ń lò lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, bóyá sísun rárà àlùfáà, àti orin Kyrie Eleison [ìyẹn orin “Olúwa, Ṣàánú fún Wa”]. Gbogbo wọn pátá la kọ́ látọ̀dọ̀ àwọn olórìṣà, a sì sọ wọ́n di mímọ́ nípa lílò wọ́n nínú Ṣọ́ọ̀ṣì.”
“Jèhófà Olódùmarè” kò sọ irú ìbọ̀rìṣà bẹ́ẹ̀ di mímọ́, kàkà bẹ́ẹ̀ ńṣe ló sọ fún àwọn Kristẹni pé: “Ẹ jáde kúrò láàárín wọn, kí ẹ sì ya ara yín sọ́tọ̀, . . . kí ẹ sì jáwọ́ nínú fífọwọ́ kan ohun àìmọ́.”—2 Kọ́ríńtì 6:14-18.