Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ mìíràn sọ pé Jésù wà nínú Hédíìsì nígbà tó kú. (Ìṣe 2:31) Àmọ́, a kò ní láti rò pé gbogbo ìgbà ni Hédíìsì àti ọ̀gbun àìnísàlẹ̀ jẹ́ ọ̀kan náà. Nígbà tó jẹ́ pé inú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀ ni ẹranko ẹhànnà náà àti Sátánì lọ, kìkì àwọn ènìyàn ni Bíbélì sọ pé ó máa ń lọ sí Hédíìsì, níbi tí wọ́n ti ń sùn nínú ikú títí di ìgbà àjíǹde wọn.—Jóòbù 14:13; Ìṣípayá 20:13.