Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ìwé Textual Criticism of the Hebrew Bible, láti ọwọ́ Emanuel Tov, sọ pé: “Nípasẹ̀ àyẹ̀wò tí a fi carbon 14 ṣe, 1QIsaa [Àkájọ Ìwé Òkun Òkú ti Aísáyà] ni a ṣírò ọjọ́ orí rẹ̀ sí àárín 202 àti 107 ṣáájú Sànmánì Tiwa (ìṣírò déètì nípa lílo ìlànà wíwo ọ̀nà ìgbàkọ̀wé ìgbàanì jẹ́: 125-100 ṣáájú Sànmánì Tiwa) . . . Ẹ̀rí fi hàn pé ọ̀nà ìgbàṣírò déètì nípa lílo ìlànà wíwo ọ̀nà ìgbàkọ̀wé ìgbàanì tí a mẹ́nu kàn yí, tí a ti mú sunwọ̀n sí i lẹ́nu àwọn ọdún àìpẹ́ yìí, tí ó sì fàyè gba ṣíṣírò déètì kanlẹ̀ ko lórí ìpìlẹ̀ fífi bí àwọn lẹ́tà ṣe rí àti bí a ṣe tò wọ́n wéra pẹ̀lú ti àwọn orísun mìíràn bí àwọn ẹyọ owó àti àwọn àkọlé tí ó ní déètì, jẹ́ èyí tí ó ṣeé fọkàn tẹ̀.”6