Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a “Ó dájú pé, gbogbo ipá ni Sátánì sà láti sáà rẹ́yìn Jésù, níwọ̀n bó ti mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run ló jẹ́, àti pé òun ni ẹni tí àsọtẹ́lẹ̀ sọ pé yóò pa òun ní orí. (Jẹ 3:15) Ṣùgbọ́n nígbà tí áńgẹ́lì Gébúrẹ́lì ń sọ fún Màríà nípa bí yóò ṣe lóyún Jésù, ó sọ fún un pé: ‘Ẹ̀mí mímọ́ yóò bà lé ọ, agbára Ẹni Gíga Jù Lọ yóò sì ṣíji bò ọ́. Nítorí ìdí èyí pẹ̀lú, ohun tí a bí ni a ó pè ní mímọ́, Ọmọ Ọlọ́run.’ (Lk 1:35) Jèhófà fi ìṣọ́ ṣọ́ Ọmọ rẹ̀. Gbogbo ìsapá láti rẹ́yìn Jésù ní rèwerèwe sì já sí pàbó.”—Ìwé Insight on the Scriptures, Apá Kejì, ojú ewé ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́jọ [868], tí Watchtower Bible and Tract Society of New York, Inc., tẹ̀ jáde.