Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a ‘Àkókò ìmúbọ̀sípò ohun gbogbo’ bẹ̀rẹ̀ nígbà tí Ọlọ́run gbé Ìjọba Mèsáyà kalẹ̀, tí ẹnì kan tó wá láti ìlà ìdílé Dáfídì Ọba sì gorí ìtẹ́. Jèhófà ṣèlérí fún Dáfídì pé ẹnì kan látinú ìlà ìdílé rẹ̀ á máa ṣàkóso títí láé. (Sáàmù 89:35-37) Àmọ́, lẹ́yìn tí Bábílónì pa Jerúsálẹ́mù run lọ́dún 607 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni, kò sẹ́nì kankan láti ìlà ìdílé Dáfídì tó ń ṣàkóso lórí ìtẹ́ Ọlọ́run. Torí pé ìlà ìdílé Dáfídì ni wọ́n bí Jésù sí, Ọlọ́run sì ti fi jọba lọ́run, òun ni Ọba tí Ọlọ́run ṣèlérí náà.