Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, ọ̀rọ̀ Hébérù tá a túmọ̀ sí “ọ̀pá” ni wọ́n máa ń lò fún igi táwọn olùṣọ́ àgùntàn fi ń da àgùntàn. (Sáàmù 23:4) Torí náà, nígbà tí Bíbélì sọ pé káwọn òbí fi “ọ̀pá” bá àwọn ọmọ wọn wí, ohun tó túmọ̀ sí ni pé kí wọ́n fìfẹ́ tọ́ àwọn ọmọ wọn sọ́nà, kì í ṣe pé kí wọ́n kanra mọ́ wọn tàbí kí wọ́n hùwà ìkà sí wọn.