Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ọ̀rọ̀ náà “ọmọ aláìníbaba” jẹ́ ká rí i pé kì í ṣe àwọn ọmọkùnrin tí kò ní baba nìkan ni Jèhófà ń bójú tó, ó tún máa ń bójú tó àwọn ọmọbìnrin tí kò ní baba. Bí àpẹẹrẹ, Bíbélì jẹ́ ká mọ bí Jèhófà ṣe dá sí ọ̀rọ̀ àwọn ọmọbìnrin Sélóféhádì lẹ́yìn tí bàbá wọn kú láìní ọmọkùnrin. Ńṣe ni Jèhófà ní kí wọ́n fún àwọn ọmọbìnrin náà ní ogún bàbá wọn. Jèhófà wá ní kí wọ́n sọ ọ̀rọ̀ yìí di òfin ní Ísírẹ́lì káwọn èèyàn má bàa máa fi ẹ̀tọ́ àwọn ọmọbìnrin aláìníbaba dù wọ́n.—Nọ́ńbà 27:1-8.