Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìràpadà náà ò lè dá Ádámù àti Éfà sílẹ̀ lọ́wọ́ ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ohun tí Òfin Mósè sọ nípa ẹni tó bá mọ̀ọ́mọ̀ pa èèyàn ni pé: “Ẹ ò gbọ́dọ̀ gba ìràpadà fún ẹ̀mí apààyàn tí ikú tọ́ sí.” (Nọ́ńbà 35:31) Ó dájú pé ikú tọ́ sí Ádámù àti Éfà torí pé ńṣe ni wọ́n yàn láti ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run, bó tiẹ̀ jẹ́ pé wọ́n mọ̀ pé ohun tí wọ́n ṣe náà ò dáa. Torí náà, wọ́n pàdánù àǹfààní tí wọ́n ní láti wà láàyè títí láé.