Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Bí Jésù ṣe bínú lọ́nà òdodo yìí, fi hàn pé ó jọ Jèhófà, ẹni tó “ṣe tán láti bínú” nítorí gbogbo ìwà ibi. (Náhúmù 1:2) Bí àpẹẹrẹ, lẹ́yìn tí Jèhófà sọ fáwọn èèyàn rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ oníwàkiwà pé wọ́n ti sọ ilé òun di “ihò tí àwọn olè ń fara pa mọ́ sí,” ó ní: “Ìbínú mi àti ìrunú mi yóò dà sórí ibí yìí.”—Jeremáyà 7:11, 20.