Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Àwọn Farisí sọ pé “ẹni ègún” làwọn tálákà tí kò mọ Òfin. (Jòhánù 7:49) Wọ́n ní ẹnikẹ́ni ò gbọ́dọ̀ kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́, kò gbọ́dọ̀ bá wọn dòwò pọ̀, kò gbọ́dọ̀ bá wọn jẹun tàbí kó bá wọn gbàdúrà. Wọ́n ní tẹ́nì kan bá gbà kí ọmọbìnrin rẹ̀ fẹ́ ọ̀kan lára wọn, ohun tẹ́ni náà ṣe burú ju pé kó gbé ọmọ ẹ̀ fún ẹranko láti pa á jẹ. Wọ́n tiẹ̀ tún gbà pé kò ní sí àjíǹde fáwọn tálákà tí kò mọ Òfin.