Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nínú àwọn ìtumọ̀ Bíbélì kan, wọ́n túmọ̀ ọ̀rọ̀ yìí sí: “Ẹ má ṣe dáni lẹ́jọ́,” àti “ẹ má ṣe dáni lẹ́bi.” Ohun téyìí túmọ̀ sí ni pé ká “má gbìyànjú láti dá àwọn èèyàn lẹ́jọ́ rárá” àti pé ká “má gbìyànjú láti dá àwọn èèyàn lẹ́bi rárá.” Àmọ́, ńṣe ni ọ̀rọ̀ táwọn tó kọ Ìwé Ìhìn Rere lò nínú ẹsẹ yìí ń sọ nípa ohun tẹ́nì kan ti ń ṣe tẹ́lẹ̀, tó sì ń bá a lọ láti máa ṣe. Torí náà, ńṣe ni Jésù ń sọ fáwọn tó ń gbọ́rọ̀ ẹ̀ pé kí wọ́n yéé hu ìwà kan tí wọ́n ti ń hù tẹ́lẹ̀.