Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí obìnrin yìí ń béèrè ìdí tí Jésù tó jẹ́ Júù fi ń bá ará Samáríà sọ̀rọ̀, ó mẹ́nu ba ìkórìíra tó ti wà láàárín àwọn ẹ̀yà méjèèjì látọdúnmọdún. (Jòhánù 4:9) Ó sì tún sọ pé àtọmọdọ́mọ Jékọ́bù làwọn èèyàn òun, èyí táwọn Júù kì í fẹ́ gbọ́ sétí. (Jòhánù 4:12) Káwọn èèyàn bàa lè mọ̀ pé ọmọ àtọ̀húnrìnwá làwọn ará Samáríà ní Jerúsálẹ́mù, ọmọ Kútà ni wọ́n máa ń pè wọ́n.