Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé ọ̀pọ̀ jù lọ lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ wà ní Gálílì nígbà yẹn, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ ìgbà tí Mátíù 28:16-20 sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ni Jésù tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jíǹde náà fara han àwọn “tí ó ju ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àwọn ará” lọ. (1 Kọ́ríńtì 15:6) Torí náà, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé àìmọye ọmọlẹ́yìn ló wà ńbẹ̀ nígbà tí Jésù gbé iṣẹ́ sísọni-di-ọmọ-ẹ̀yìn lé àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ lọ́wọ́.