Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Jésù tún sọ pé àlùfáà àti ọmọ Léfì ń bọ̀ “láti Jerúsálẹ́mù,” èyí tó túmọ̀ sí pé wọ́n ti kúrò ní tẹ́ńpìlì. Nítorí náà, kò sí àwíjàre kankan fún bí wọn ò ṣe ran ẹni tó ń kú lọ yẹn lọ́wọ́. Wọn ò lè sọ pé torí bó ṣe dà bí ẹni pé ọkùnrin tó bọ́ sọ́wọ́ àwọn ọlọ́ṣà náà ti kú ni ò jẹ́ káwọn ṣaájò rẹ̀, nítorí pé táwọn bá fọwọ́ kan òkú, kò ní jẹ́ káwọn lè ṣiṣẹ́ nínú tẹ́ńpìlì fún ìwọ̀n àkókò kan.—Léfítíkù 21:1; Númérì 19:16.