Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Lọ́jọ́ yẹn nìkan ṣoṣo, ẹ̀ẹ̀méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni wọ́n tutọ́ sí Jésù lára, àwọn aṣáájú ìsìn ló kọ́kọ́ ṣe bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ ogun Róòmù tó wá ṣe tiwọn. (Mátíù 26:59-68; 27:27-30) Kódà gbogbo bí wọ́n ṣe fàbùkù kàn án tó yìí kò mú kó bọ́hùn, ó fara dà á, ó sì tipa bẹ́ẹ̀ mú àsọtẹ́lẹ̀ ṣẹ, èyí tó sọ pé: “Ojú mi ni èmi kò fi pa mọ́ fún àwọn ohun tí ń tẹ́ni lógo àti itọ́.”—Aísáyà 50:6.